Ekiti APC Primary: Abiodun Oyebamiji ni APC dìbò yàn gẹ́gẹ́bí olùdíje fún ipò gómìnà l'Ekiti

Aworan Oyebanji

Oríṣun àwòrán, Facebook/Biodun Oyebanji

Eto idibo abẹnu ẹgbẹ oṣelu All Progressives Congress nipinlẹ Ekiti ti pari.

Abiodun Oyebanji si ni oludije to jawe olubori fun ipo gomina labẹ ẹgbẹ oselu APC nipinlẹ naa.

Oyebamiji ni ibo ẹgbẹrun mọkanlelọgọrun ati ẹẹdẹgbẹrin o le mẹta, (101703) lati bori ero idibo yiyan oludije fun ipo gomina naa eleyi to ti fa ọpọlọpọ awuyewuye.

Awọn oludije meje ti kọkọ fariga pe awọn ko ni kopa ninu eto idibo naa ayafi ti wọn ba wọgile eto ọhun ki wọn si mojuto awọn ẹhonu wọn gbogbo.

Amin iyasọtọ kan

Bi esi ibo naa ṣe lọ niyi:

Iye awọn ọmọ ẹgbẹ APC ni ipinlẹ Ekiti -183,560

Iye awọn to ṣe ayẹwo lati dibo- 107877

Iye awọn to dibo- 104983

Iye ibo ti awọn oludije kọọkan gba

Bamidele Faparusi - 376

Kayode Ojo- 767

Michael Ọpẹyẹmi Bamidele- 760

Adeyeye - 691

Olufemi Bamiṣile- 400

Abiodun Oyebamiji- 101, 703

Amin iyasọtọ kan

Biodun Oyebanji,Kọmiṣana, olukọ fasiti tẹlẹ to fẹ ṣe Gomina bayii:

Ninu ifọrọwanilẹnuwo kan to ṣe laipẹ yi pẹlu ileeṣẹ iroyin This Day,Biodun Oyebanji sọ pe ohun to wu oun ni ki Gomina Kayode Fayemi ṣatilẹyin fun un ninu idibo Gomina.

Ni bayi to ti wa jaweolubori gẹgẹ bi oludije ẹgbẹ oṣelu APC ninu idibo Gomina, ala naa ti n sunmọ imuṣẹ bọ diẹdiẹ.

Ṣaaju ko to du ipo yi, Biodun Oyebanji ti di ipo Kọmisana mu nipinlẹ Ekiti to si tun ṣe akọwe agba si ijọba ipinlẹ Ekiti.

Aworan Oyebanji

Oríṣun àwòrán, Facebook/Biodun Oyebanji

Gẹgẹ bo ti ṣe sọ ninu ifọrọwanilẹnuwo taa n wi yi, o ni ''mo ti wa ni ijọba fun ọdun mọkanla ninu ọdun mẹẹdọgbọn ti a le sọ pe wọn ti da ipinlẹ Ekiti silẹ''

Labẹ ijọba Gomina Kayode Fayemi, Biodun Oyebanji ti baa ṣiṣẹ pọ ni saa meji to lo lori oye ni ipadabọ rẹ gẹgẹ bi Gomina ipinlẹ Ekiti.

Bi eeyan ba wo eleyi, o jọ pe ọrọ tawọn oludije iyoku n sọ pe ayanfẹ Gomina Fayemi ni Oyebanji fẹ jọ bi ootọ botilẹ jẹ pe Gomina Fayemi ko ti figba kan polongo fun.

Ki ni awọn oludije yoku n sọ nipa esi idibo yi

Ohun ti wọn sọ ṣaaju ati lasiko idibo naa to waye lỌjọbọ ni a le fidi rẹ mulẹ.

Ninu awọn oludije mẹjọ fun ipo yi labẹ asia APC awọn meje sọ pe awọn ko le kopa ninu eto idibo naaa nitori o ni ọwọ madaru ninu.

Wọn fẹsun kan awọn eleto idibo naa ti ijọba yan lati ba awọn eleyi to wa lati olu ileeṣẹ ẹgbẹ ni Abuja pe wọn n gbe lẹyin Biodun Oyebanji.

Ọrọ yi kawọn lara debi pe awọn alatilẹyin wọn ṣe iwọde ifẹhonuhan si olu ileeṣẹ ẹgbẹ APC ni Ekiti ti wọn si sọ pe eto idibo naa ko le yanrantin fun idi eyi.

Bayi ti idbo ti pari ti wọn si ti kede Oyebanji gẹgẹ bi oludije, a o maa reti boya awọn oludije yoku yoo gbaruku ti tabi wọn yoo kọri si iwaju igbimọ ti yoo gbẹjọ ẹhonu lori idibo naa.

O ku sọwọ igbimọ ẹhonu esi idibo-Oyebanji

Lasiko to n ba awọn akọroyin sọrọ ni ile rẹ to wa ni Ikogosi Biodun Oyebanji sọ pe inuoun dun si eto idibo naa.

O gbosuba kare fun Gomina Mohammed Badaru ipinlẹ Jigawa to dari eto naa to si ni idibo naa ko ni aayẹ gẹgẹ bi awọn akẹgbẹ rẹ to ku ti ṣe ọ.

Gomina Muhammad Badaru to n kede esi idibo abẹnu APC Ekiti

O ni igbimọ kotẹmilọrun APC ni o wa ku sọwọ wọn bayi lati gbọ eyikeyi ikunsinu tawọn eeyan le ni lori eto idibo naa.

''Ilana ẹgbẹ wa faaye silẹ fawọn to ba fẹ pẹjọ kotẹmilọrun.Wn ni ẹtọ lori ero wọn ṣugbọn ẹgbẹ ni yoo sọ ibi ti ọrọ yoo ja si''