Baba Suwe: Adesola Omidina ní òun ti bẹ̀rẹ̀ èrè Suwe Family lórí ayélujára tí orúkọ bàbá òun kò fi ní parun

Adesola ati Baba Suwe

Oríṣun àwòrán, Omo_Omidina/Instagram

Ọkan lara awọn ọmọ Baba Suwe, Adesola Morenikeji Ibrahim Omidina, naa ti sọrọ nipa igbe aye ati iku baba rẹ.

Nigba toun naa n bawọn akọroyin sọrọ lasiko isinku naa, Adesola ni gbogbo eeyan ni oun n ki pe wọn seun fun atilẹyin baba awọn.

O ni onisowo ni oun, ti oun si tun ni awọn oju opo lori ayelujara ti oun ti n se agbelaruge tiata, paapaa isẹ baba oun ti oun pe ni 'Suwe Family'.

Àkọlé fídíò, Àwọn òṣìṣẹ́ Adedoyin jẹ́wọ́ fún wa pé àwọn pa àbúrò mi, ọ̀gá Adedoyin sì mọ̀ síi - Ẹ̀gbọ́n Timothy Adegoke

"Emi ko ri Baba Suwe bii baba mi nigba to wa nile aye, mo rii bi alawada, mo si maa n pe ni alagbada gbogbonse (Universal Comedian).

Igbakuugba ni baba mi maa n pa eeyan lẹrin, ti mo ba si wo baba mi lasan, maa rẹrin, ti mo si ti se ọpọ akọsilẹ nipa baba mi.

Àkọlé fídíò, Baba Suwe: Bi eto isinku Babatunde Omidina se lọ ree

Ọpọ eeyan lo maa n ni mo jọ baba mi amọ ba se sunmọra to, bẹẹ naa ni a se maa n ja, mo si nifẹ baba mi pupọ pupọ.

Gbogbo eeyan si lo le jẹri si pe mo fi ọpọ akoko mi ati igbe aye mi jin fun baba mi nigba to wa laye, amọ o wu Ọlọrun lo mu lọ."

Adesola wa fi ọwọ sọya pe oun nigbagbọ pe orukọ baba oun ko ni parun, oun si ni igbagbọ ninu Ọlọrun ati atilẹyin awọn osere tiata, alagbata fiimu atawọn oludari ere pe yoo see se.

Àkọlé fídíò, Gbọ́ ohun ti àwọn òṣèré tíátà Yoruba sọ fún BBVC nípa Baba Suwe