Bola Tinubu: Mo dúpẹ́ pé mo padà délé láyọ̀

Asiwaju Bola Tinubu

Oríṣun àwòrán, Bola Tinubu

Asaaju ẹgbẹ oselu APC, Asiwaju Bola Tinubu ti n dupẹ lọwọ Ọlọrun pe o da oun pada si orilẹede Naijiria ni alaafia.

Tinubu, ẹni to ti kuro lorilẹede yii lati osu mẹta sẹyin lati lọ se isẹ abẹ nilu London lo n dupẹ bẹẹ nile ijọba ni Marina nibi apejẹ ikinni kaabọ ti ijọba ipinlẹ Eko se fun.

Tinubu ni "Ori mi wu amọ inu mi dun pe mo pada sile. Ọlọrun lo n fun ni ni iye, oun naa si lo le gba a.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ọlọrun nikan lo le gba ẹmi mi tabi fun mi ni iye, ara mi si ti le koko pada, mo si dupẹ pe mo pada sile pẹlu alaafia pipe.

Tinubu wa dupẹ lọwọ awọn eeyan to seto ikinni kaabọ naa fun to si gbadura fun wọn pe Ọlọrun yoo dahun gbogbo ohun to n wu wọn lọkan.

Àkọlé fídíò, Olota Of Ota: N kò fara mọ́ ìyapa Nàíjíríà, ìṣèjọba ẹlẹ́kùnjẹkùn ní ọ̀nà àbáyọ
Amin iyasọtọ kan

'Bola Tinubu ńbọ̀ ní Nàìjíríà láìpẹ́, àmọ́ kò tíì dé'

Asiwaju Bola Tinubu

Oríṣun àwòrán, other

Bola Tinubu ko tii kuro lorilẹede Gẹẹsi nibi to wa to ti n fun ara ni isinmi.

Ọrọ yii ni agbẹnusọ rẹ, Tunde Rahman fi dahun ibeere ti BBC News Yoruba taare sii lori aworan ati fidio to n ja rainrain lori ayelujara pe eekan ẹgbẹ oṣelu APC naa ti wa sile tabi gbera lọ si orilẹede miran fun iwosan.

Ọgbẹni Tunde Rahman ni laipẹ laijina ni Aṣiwaju Bọla Ahmed Tinubu yoo de si Naijiria ṣugbọn lọwọ yii Jagaban ko tii pada si Naijiria.

"Aworan fidio ti wọn n gbe kiri yẹn kii ṣe tii isinyi o. Ti igba pipẹ sẹyin ni ti a n lọ si orilẹede Saudi Arabia ni oṣeeṣe ko jẹ".

O fi kun un pe ariwo ti awọn eeyan n pa nipa ilera Aṣiwaju Bọla Tinubu ko n ṣe ara rẹ nitori pe ohun kan ṣoṣo to ṣee naa ni ipenija orokun rẹ; orokun yii lo si lọ ṣe iṣẹ abẹ le lori lẹyin eyi ko si nnkankan to ṣee.

Akoko iwosan iṣẹ abẹ naa lo n la kọja, to si ti gbadun bayii.

"Fun bii nnkan bi ọsẹ mẹrin si marun sẹyin ko lo igi gan lati fi rin mọ."

Aworan to n fa ariyanjiyan naa

Oríṣun àwòrán, other

Sẹnetọ ana, Shehu Sani wa lara awọn eekan to gbe iroyin naa si ori ikanni ayelujara wọn pe agba oṣelu naa ti pada to si kii ku oriire araya.

O ti le ni nnkan bii oṣu meji bayii ti Aṣiwaju Bọla Ahmed Tinubu ti fi orilẹede Naijiria silẹ fun itọju ara rẹ loke okun.

Lati igba yii wa si ni ọpọlọpọ awọn oloṣelu ninu eyi ti ko yọ aarẹ orilẹede Naijiria, Mohammadu Buhari gan silẹ atawọn gomina kaakiri orilẹede Naijiria pẹlu to rinrinajo lọ oke oku si lọ n bẹẹ wo.

Àkọlé fídíò, 'Mo ti gba kádàrá lórí bí Ọlọrun ṣe dá mi'