Olojo Festival 2021: Aisha Yesufu ní káwọn aráàlú yé gbé ohun tó yẹ kí wọn ṣe, kọ́ Ọlọ́run lọ́rùn

Oríṣun àwòrán, Ooni of Ife
Lọjọ Aje ni iroyin jade pe Ọọni ile Ife, Ọba Adeyẹye Ogunwusi Ọjaja keji ti wọ ipebi fun ọjọ meje, gẹgẹ bi ara eto ayẹyẹ ọdun Ọlọjọ to maa n waye ni ọdọọdun.
Ooni, ninu ọrọ to fi ransẹ si araalu, ko to wọ ipebi lọ fun ọjọ meje salaye pe, ara ohun ti oun yoo ṣe lasiko naa ni lati gbadura ki Eledumare fọwọkan awọn oloṣelu ati adari gbogbo ninu.
Amọsa, ọrọ naa ti n fa oniruru ariyanjiyan laarin awọn ọmọ Naijiria. Lara awọn to ti sọrọ lori rẹ ni eekan ajafẹtọ araalu ni Naijiria, arabinrin Aisha Yesufu; ẹni to ni awada nla lọrọ naa jẹ fun oun nigba ti oun gbọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ẹgbẹ́ ìlànà ọmọ Oodua fi ìròyìn ayọ̀ ránṣẹ́ lórí Sunday Igboho
- "Tí Sunday Igboho, Nnamdi Kanu bá bọ́ sínú APC, wọn yóò gbá ìtúsílẹ̀''
- Seyi Makinde kúró lẹ́gbẹ́ PDP, ìyà tó o fi jẹ wá tó - Igun PDP Oyo
- Afurasí Fulani ti pa aráàlú mi bíi 50, jó ile 254 níná - Oríadé kan figbe ta
- Ìdí rèé lórí bí mo ṣe di oníyàwó márùn-ún, ẹjọ́ mi kọ́ - Ọkọ Lizzy Anjorin
- Obìnrin kan wọ ‘Wedding Gown’ láti wá ọkọ lójú pópó. Òpin ayé dé!
- Gbogbo òṣìṣẹ́ ọba l‘Osun, abẹ́rẹ́ Covid-19 di ọ̀rànyàn fún yín bíbẹ́ẹ̀ kọ́... Oyetola
- Ewú n bẹ̀ nínú ṣíṣe ádùrá nínú igbó, kẹ́ má bà kó sọ́wọ́ ajínigbé - ọlọ́pàá ṣèkìlọ̀
- Sanwo-Olu buwọ́lu òfín máfi ẹran jẹko láàrín ìgboro l'Eko
- PDP Oyo sọ̀rọ̀ lórí pé Seyi Makinde ń lọ sẹ́gbẹ́ APC
O ni kawọn ómọ Naijiria yee reti ki Olorun wa ba wọn ṣe ohun ti awọn funra wọn le ṣe.
Loju Aisha Yesufu, Olorun ti ṣe eyi to ju ninu ọrọ nipa fifun wa ni anfani ati agbara lati dibo yan awọn aṣiwaju rere, sibẹ ọpọlọpọ ni kii lo agbara naa.
Pẹlu bi eto idibo apapọ ti ọdun 2023 se n bọ lọna bayii, o ni ki awọn ọmọ Naijiria lo anfani ati agbara naa lo ja julọ.

Ẹ wo ohun tí Ooni yóò ṣe fáwọn olóṣèlú bó se wọ ìpèbí lọ fọ́dún Ọlọ́jọ́

Oríṣun àwòrán, Ooni of Ife Facebook
Gẹgẹ bi ara igbesẹ fun ayẹyẹ ọdun Ọlọjọ ti Ọdun yii, Ọọni ile Ifẹ, Ọba Adeyẹye Enitan Ogunwusi, Ọjaja keji ti wọ ipebi lọ lọjọ Aiku, nibi ti yoo wa fun ọjọ meje.
Itumọ ọdun ọlọjọ ni ọjọ ti ọjọ kọkọ bẹrẹ si ni jẹ ọjọ. Iyẹn ni pe ọjọ ti ojumọ kọkọ mọ lorilẹ aye.
Ninu iṣẹṣe ilu Ile Ifẹ, ọdun ọlọjọ ni wọn ya sọtọ lati ṣe ayajọ ọjọ ti Olodumare kọkọ da ile aye.
Ninu ọrọ rẹ ki o to wọ inu ipebi lọ Ọọni Ogunwusi ni ko si ohun meji ti oun nilo lati ṣe ninu ipebi ọlọjọ meje naa ju gbigba adura fun idagbasoke orilẹede Naijiria.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Obìnrin kan wọ ‘Wedding Gown’ láti wá ọkọ lójú pópó. Òpin ayé dé!
- Ìwà ọ̀daràn àti òmùgọ̀ ní kí Nàíjíríà jẹ gbèsè kún gbèsè - Obasanjo
- Jonathan, má yẹ̀yẹ́ ara rẹ láti díje ìbò ààrẹ 2023 - Ọ̀gá ẹgbẹ́ àwọn gómìnà kìlọ̀
- A kìí ṣọ̀rẹ́ èrò ká yọ̀ lọ̀rọ̀ Fani-Kayode, ajá rẹ̀ kò mọ ẹni a kìí gbó mọ́ - Salihu Lukman
- Tinubu là ń dúró dè láti sọ ìpinnu wa fétò ìṣèlú 2023 - Akeredolu
- Láì sí ẹ̀kùn àríwá, òfo ní ìpínlẹ̀ Eko, Rivers lórí owó ọjà - Masari
- Buhari, káàbọ̀ sí Amẹ́ríkà àmọ́ ohun tà ń fẹ́ rèé - Yoruba Nation
Olori ọba alade naa ni bi awọn ọmọ Naijiria ba woye daadaa, ọpẹ lo yẹ Naijiria paapaa pẹlu ajakalẹ arun COVID-19 to gbode lagbaye ṣugbọn ti ọṣẹ rẹ ṣu n mọ niwọnba ni Naijiria.
O ni sibẹ awọn adari ko gbọdọ sinmi lati rii pe ignayegbadun awọn araalu jẹ wọn logun. Ọọni Ogunwusi fi kun un pe idi gan niyi ti oun yoo fi lo ọjọ kẹfa ninu ipebi lati gbadura fawọn aṣiwaju ni Naijiria.
"Wiwọ ipebi ṣaaju ọdun ọlọjọ ṣe pataki pupọ, idi si niyi ti mi o le fi ṣere rara nitori ajogunba lọwọ awọn baba nka mi lati ẹgbẹkẹgbẹ ọdun sẹyin ni."
Bakan naa lo fi kun pe oun yoo lo asiko naa lati gbadura si Eledumare ko fọwọ tọ awọn oloṣelu lọkan ki wọn lee dẹkun fifi aye araalu ta keke, ki wọn si lee maa tẹti si awon ohun gbogbo to n dun araalu lọkan.


















