Husband Searcher: Obìnrin náà ní òun yóò san owó orí ọkọ òun, ti òrùka ìgbeyàwó

Oríṣun àwòrán, Screen Shot
Ara meeriri kan ree o, a ri ori ologbo lori atẹ, Yoruba sa ni airin jinna ni airi abuke ọkẹrẹ, bi eeyan ba rin jinna, yoo ri ibi ti wọn ti n fi odo ibulẹ jẹun.
Bo se ri ree pẹlu obinrin wundia kan to wọ asọ igbeyawo maa kiri oju popo pe oun n wa ọkọ ti yoo fẹ oun sile, eyi to fun ọpọ eeyan niran wo.
Isẹlẹ yii si lo waye lagbegbe Buza nilu Dares Salam lorilẹede Tanzania, nigba ti obinrin naa gbe akọle kan lọwọ lati salaye pe oun n wa ọkọ ti yoo fẹ oun nitori ọjọ ti n lọ lori oun.
- Tẹgbọn-taburo se igbeyawo ni Anambra
- Iléẹjọ́ wọ́gilé ìgbeyàwó nílànà ẹ̀sìn Islam pé kò bófin mu
- Iwa nabi tu igbeyawo ọgbọn ọdun ka
- Tó o bá ṣàdéhùn ìfẹ́ tó ò mú u ṣẹ, ẹ̀wọ̀n lo fi ń ṣeré
- N kò fẹ́ kí ojú ti ọkọ mi, ni mo ṣe gbe oyún wá láti ìta - Abilékọ
- Iléẹjọ́ tú ìgbéyàwó ọdún méjé ká nítorí àìnáání ara ẹni
Fidio kan to gba awọn oju opo ayelujara kan lo se afihan obinrin naa pẹlu akọle to n salaye iru ọkọ to fẹ fẹ.
Gẹgẹ bi akọle naa ti wi, obinrin naa ni oun n wa ọkọ ti ọjọ ori rẹ wa laarin ogun ọdun si aadọrin ọdun, ti oun si setan lati san owo ori iru ọkunrin naa.
Bakan naa lo fi kun pe oun ti ra oruka igbeyawo pamọ eyi ti oun ati ọkunrin to ba gba lati fẹ oun yoo lo lati se igbeyawo.
Obinrin naa to wọ asọ igbeyawo tun sisọ loju rẹ pe ẹgbẹrun lọna mejilelogoje sile owo ilẹ Tanzania.
O fikun pe ẹlẹsin Kristiẹni ni oun amọ oun setan lati di ẹlẹsin musulumi to ba jẹ ọkunrin to fẹ fẹ oun jẹ ẹlẹsin Islam.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìwà ọ̀daràn àti òmùgọ̀ ní kí Nàíjíríà jẹ gbèsè kún gbèsè - Obasanjo
- Jonathan, má yẹ̀yẹ́ ara rẹ láti díje ìbò ààrẹ 2023 - Ọ̀gá ẹgbẹ́ àwọn gómìnà kìlọ̀
- A kìí ṣọ̀rẹ́ èrò ká yọ̀ lọ̀rọ̀ Fani-Kayode, ajá rẹ̀ kò mọ ẹni a kìí gbó mọ́ - Salihu Lukman
- Tinubu là ń dúró dè láti sọ ìpinnu wa fétò ìṣèlú 2023 - Akeredolu
- Láì sí ẹ̀kùn àríwá, òfo ní ìpínlẹ̀ Eko, Rivers lórí owó ọjà - Masari
- Buhari, káàbọ̀ sí Amẹ́ríkà àmọ́ ohun tà ń fẹ́ rèé - Yoruba Nation
- Wo ohun tó ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ tí Sunday Igboho gbàlejò Fani-Kayode
- Òkú obìnrin tí mò ń lọ wẹ̀ yọ sí mi, ohun tó sọ rèé - Agbókùújó
- Bí egungun bá há ọ lọ́fun, wo ohun méje tó ṣe láti yọ́
- Wọ́n fipá bá mi lòpọ̀ tán, díẹ̀ ló kù - Nkechi Blessing
- Mó kópa nínú fíímù fún ọjọ́ mẹ́wàá, mo gba ₦1,000 - Lateef Adedimeji
O ni irufẹ ọkunrin naa gbọdọ ni ibẹru Ọlọrun lọkan, ko si tun ni itẹriba pẹlu, to si tun gbọdọ ni ifẹ oun pupọ.
Obinrin ọhun wa fi ọwọ gbaya pe owo ko ni jẹ isoro awọn nitori Ọba Oke fi owo da oun lọla pupọ.
Yatọ si eyi, obinrin naa ni oun yoo maa lọ kaakiri awọn agbegbe to wa lorilẹede naa, lati kede pe oun n wa ade ori.



















