Divorce in Nigeria: Abilékọ kan ṣàlàyé lórí ìdí tó fi gb'oyún láti ìta wá sọ́ọ̀dẹ̀ ọkọ

Oríṣun àwòrán, The Star
Abilekọ kan to n gbe ilu Ibadan, Toyin Bello ti sọ ohun to ri lọbẹ to fi waro ọwọ, lori bi o ti gba ki ọkunrin mii fun un loyun lọọdẹ ọkọ rẹ.
Nigba to n jẹjọ nile ẹjọ kọkọ-kọkọ niluu Ibadan, Bello beere pe ki ileẹjọ tu igbeyawo ọdun mẹrindinlogun pẹlu ọkọ oun ka, nitori aileṣe bii ọkunrin rẹ.
Bello ti kọkọ fẹsun kan ọkọ rẹ pe, o fi Ibalopọ dun oun fun ọdun mẹwaa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- "APC àti PDP ń dìtẹ̀ láti yọ Seyi Makinde ní 2023, ẹ gbàdúra fun kó gúnlẹ̀ ayọ̀"
- EFCC gba ọ̀pọ̀ owó àti dúkìá, ó tún fọwọ́ òfin mú afurasí 865 lọ́dún 2020
- Ìwọ́de ńlá míì ń bọ̀ ní March, tí December 2021 yóò sì gbóná fáwọn ọ̀jẹ̀lú olóṣelú - Alfa sọ àsọtẹ́lẹ̀
- Njẹ́ ẹ ti gbọ́ nípa àríyá oníhòhò àti ìbálòpọ̀ tó fẹ́ wáyé ní Kaduna lásìkò ọdún?
- Àjọ NIMC ti fún MTN, Glo, 9mobile àti Airtel ní àṣẹ láti bẹ̀rẹ̀ ìforúkọsílẹ̀ fún NIN
- Wo iye àwọn ìpínlẹ̀ tó fòfin de ìsìn àìṣùn ọdún ní ṣọ́ọ̀ṣì
- Àwọn àjàkálẹ-àrùn tó ti wáyé rí ṣáájú Coronavirus
- Ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn mẹ́ẹ̀dógún wọ gàù ọlọ́pàá ségí ní Eko
- Ikú Adewole Oniluola, tó ní ẹ̀bùn ìlù lílù jùlọ lágbàyéé, yóò nípa lórí Yorùbá - Tunde Kelani
Obinrin naa sọ fun ileẹjọ pe, oun gbe igbesẹ lati gb'oyún lati ita nitori itiju airọmọ bi.
"Mi o fẹ ki oju ti ọkọ mi nitori airọmọbi lo jẹ ki n gba oyun lati ita," arabinrin Bello lo sọ bẹẹ.
Bello ni ọkọ oun tun fẹ ṣeku pa oun ko le jogun ile oun.
"Mo kuro nile lati maa gbe ni ṣọọṣi lagbegbe Asi n'Ibadan, Oluwa mi, mi o le maa fi akoko mi ṣofo mọ pẹlu Dotun, ọjọ ti n lọ lori mi. Ẹ jọwọ, ẹ tu igbeyawo yii ka," Bello rọ ileẹjọ.
Henry Agbaje to jẹ aarẹ ileẹjọ naa tu igbeyawo ọhun ka, o si pàṣẹ pe ki Dotun kuro ninu ile ti wọn jọ n gbe laarin ọjọ méje.
Amọ, Ọgbẹni Dotun tako idajọ naa, o si rọ ileẹjọ lati ba oun bẹ iyawo oun.
Dotun ni lootọọ ni pe oun ni ailera lati fun obinrin loyun, ṣugbọn iyawo oun naa ti ilẹkun mọ ri, ko jẹ ki oun wọle tọ ọ.














