Covid-19: Ìjọba Osun ní abẹ́rẹ́ covid-19 ti di dandan fáwọn òṣìṣẹ́ ìjọba àtàwọn elétò ìlera

Gomina Oyetola n gba abẹrẹ Covid-19

Oríṣun àwòrán, Osun State Government

Gomina ipinlẹ Osun, Adegboyegba Oyetola ti paa laṣẹ fun gbogbo awọn alabaṣiṣẹ pọ rẹ, awọn oṣiṣẹ ijọba, awọn eleto ilera atawọn nipinlẹ naa lati gba abẹrẹ ajẹsara covid-19.

Gomina Oyetola ṣalaye pe igbesẹ yii jẹ ọkan lati dẹkun ajakalẹ arun coronaviris nipinlẹ naa.

Gomina sọrọ yii ninu atẹjade kan ti olori awọn oṣiṣẹ nipinlẹ Osun fi sita.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Oyetola sọ ninu atẹjade naa pe ijọba ipinlẹ Osun ṣetan lati ge ọwọja covid-19 kuru nipinlẹ Osun.

O ni idi niyii ti ijọba fi pese abẹrẹ coronavirus lawọn ileeṣẹ eto ilera kaakiri ipinlẹ Osun fawọn oṣiṣẹ lati le gbaa.

Àkọlé fídíò, Sabaa Akintola: Pẹ̀lú ẹsẹ̀ kan, mo le gun kẹ̀kẹ́, lúwẹ̀ẹ́ tàbí rán aṣọ pẹ̀lú ẹ̀kọ́ dókítà

Gomina Oyetola ni gbigba abẹrẹ yii lo le daabo bo awọn oṣiṣẹ atawọn araalu lọwọ arun covid-19 to n ṣọṣẹ ni Naijiria.

Ijọba ipinlẹ Osun sọ ninu atẹjade ọhun gbogbo awọn ti ọrọ kan ko gbọdọ kọ eti ikun si aṣẹ gomina yii.

Bakan naa ni gomina rọ awọn oṣiṣẹ lati maa tẹle ilana ati dẹkun covid-19 bii ibomu wiwọ ati titakete siraẹni.

Gomina tun rọ wọn pe ki wọn yago fun apejọ ọpọ eeyan, ki wọn si maa fọ ọwọ wọn deedee pẹlu ọsẹ ati omi.

Oyetola rọ gbogbo awọn olori ileeṣẹ ijọba, ile ẹkọ giga, ati ijọba ibilẹ lati ri pe awọn oṣiṣẹ to wa labẹ wọn pa aṣẹ ijọba yii mọ.

Àkọlé fídíò, Yoruba Nation: Kò sí ìdí tí à ó fi bínú sí Akeredolu lórí ọ̀rọ̀ Yorùbá Nation