Yoruba Self Determination: Àgbáríjọpọ̀ ẹgbẹ́ Yorùbá gbẹ́ná wojú Gumi lórí àbẹ̀wò rẹ̀ sí ìlú Sunday Igboho

Sunday Igboho ati Sheik Gumi

Agbarijọpọ awọn ẹgbẹ itẹsiwaju ọmọ Yoruba ti bẹnu atẹ lu abẹwo ti Sheikh Gumi ṣe si ilu Igboho ni ipinlẹ Oyo.

Lopin ọsẹ to kọja ni Sheikh Gumi ati awọn ikọ kan lati Ariwa Naijiria lọ si ilu Igboho ti wọn si fi fọnran fidio kan sita nipa abẹwo wọn.

Ilu Igboho ni ilu abinibi gbajugbaja ajafẹtọmọniyan ilẹ Yoruba ni, Sunday Adeyemo ti gbogbo eeyan mọ si Sunday Igboho.

Ninu fọnran fidio naa Gumi ati Ọjọgbọn Yusuf sọ pe awọn wa ni Igboho nibi ti awọn ti ri tawọn eeyan n gbe igbe alaafia.

Awọn mejeeji ni awọn ko ri idi ti awọn kan bi Sunday Igboho yoo maa pe fun iyapa Naijiria dipo ki awọn eeyan Naijiria gbe pọ pẹlu alaafia.

Ọrọ ti wọn sọ yi lo mu ki agbarijọpọ ẹgbẹ awọn ọmọ Yoruba sọ pe ero aburu ni Gumi ni lọkan pẹlu abẹwo rẹ to ṣe si ilu Igboho.

Dokita Steven Abioye to gbẹnusọ fawọn ẹgbẹ yi ni awọn iwa fifa ori apa kan da apa kan si yi ko ni ṣiṣẹ nilẹ Yoruba lọtẹ yi.

O ni ''Abẹwo Gumi yi si ilu Igboho lọwọ aburu ninu. Iṣesi awọn Fulani to kun fun ète lo n ṣe. Erongba wọn pẹlu abẹwo yi kii ṣe eyi to mọ''

Abioye tẹsiwaju pe ''bayi ti wọn ri pe saa ijọba Buhari ti fẹ tan,wọn n wa ọna tawọn eeyan yoo fi foju daada wo wọn ki aarẹ Fulani mi ba le bọ sipo''

O ni iru etekete bayi ko le e mu awọn ọmọ Yoruba mọ bi tatẹyinwa.

''Ki lo de to fi ṣe pe ilu Igboho ni Gumi lọ ṣe abẹwo si dipo ilu miran?Nitori pe Sunday Igboho gbe orukọ ilu naa ga ni.Gbogbo ọgbọn ti wọn n da la ti mọ pata''