Nnamdi Kanu: Sunday Igboho ní mímú aṣaájú IPOB kò lè dí ìwọ́de Yoruba Nation Eko lọ́wọ́

Oríṣun àwòrán, other
Ọkan gboogi lara awọn to n ja fun idasilẹ orilẹede Yoruba, Oloye Sunday Igboho ti sọ pe bi ọwọ ijọba ṣe tẹ aṣiwaju ipe fun idasilẹ orilẹede Biafra, Mazi Nnamdi Kanu, ko ni idiwọ kankan fun ohun ti oun n ja fun.
Lọjọ Iṣẹgun ni iroyin jade pe ọwọ ijọba ti tẹ Nnamdi Kanu, ti wọn si ti fi si ahamọ lẹyin ti wọn foju rẹ ba ileẹjọ giga apapọ nilu Abuja.
Eyi mu ki ọpọ awọn ololufẹ Sunday Igboho o maa ko aya soke pe, o ṣeeṣe ki ijọba maa gbiyanju ati fi ṣikun ofin gbe Igboho pẹlu.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Eré wa ni kẹ wò, ẹ má wo aṣemáṣe àwa onítíátà - Olaiya Igwe
- Àwọn àgbà Yorùbá sọ̀rọ̀ lórí ìbẹ̀rù pé wọ́n le gbé Sunday Igboho lẹ́yìn tọ́wọ́ tẹ Nnamdi Kanu
- Èèmọ́ wọ̀lú, ta ló yìnbon pá Babalawo àti ẹlòmíì, tí ọ̀pọ̀ sì fara pa ní Ajaawa?
- Bíṣọ́ọ̀bù Enugu ní obìnrin ni wọ́n fi mú Nnamdi Kanu
- Ẹni tó bá tàbùkù àgbà níta, ti ń bú òbí rẹ̀ nílé tẹ́lẹ̀ - Yomi Fabiyi
- Ọjọ́ mẹ́rin ni mo fi bẹ Princess pé kí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha má di ẹjọ́ - Iya Rainbow
- Ọlọ́pàá ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ Interpol ṣèrànwọ́ fún ìjọba àpapọ̀ láti mú Nnamdi Kanu
- Orí àgbá ẹ̀tù láwọn èèyàn Ibarapa jókòó lé, wàhálà ń bọ̀ - OPC mẹ́ta tó gba ìdáǹdè
- Jide Kosoko, tí mo bá tú àṣírí rẹ, àwọn ọmọbìnrin rẹ yóò dọwọ́ bojú - Nkechi Blessing yarí
Amọṣa, Igboho Ooṣa, gẹgẹ bi ọpọlọpọ awọn ololufẹ rẹ ṣe maa n pe e sọ pe, ẹru ko ba oun o ati pe eyi ko ni idiwọ kankan lati ṣe fun iwọde ipe fun 'Yoruba Nation".
Sunday Igboho lo fi ọrọ yii lede lati ẹnu agbẹnusọ rẹ, Olayomi Koiki.
Koda, o ni iwọde naa ti wọn ti seto pe yoo waye ni ilu Eko lọjọ Satide, ọjọ kẹta oṣu Keje ọdun 2021, yoo lọ, gẹgẹ bo se wa ni akọsilẹ.
Bakan naa lo fi kun un pe, gba-gba-gba loun wa lẹyin Nnamdi Kanu ati pe atilẹyin oun ko yẹ gẹrẹ ninu atilẹyin oun fun ipe fun orilẹede Biafra.
N ko lagbara lati ba ijọ̀ba ja:
Bakan naa ni Igboho ti kede ninu fidio kan to n ja lori ayelujara pe oun ko ni agbara kankan lati ba ijọba apapọ ja tabi ijọba ibilẹ lasan.
O ni Ọlọrun ni yoo ja fun idasilẹ orilẹede Yoruba Nation ati iran Yoruba lapapọ, ki wọn le ya kuro lara Naijiria.
O ni oun ko gbagbọ pe ẹnikẹni n dunkoko lati di awọn ajija gbara naa lọwọ lati wa silu Eko fun iwọde lọjọ Satide to n bọ.

Oríṣun àwòrán, Olayomi Koiki/Facebook
O ni ti eyi ba jẹ otitọ, ki ẹni naa se fidio ara rẹ sita, ko si sọ awọn ọrọ naa, eyi ti yoo jẹ kawọn ri otitọ ọrọ dimu.
Igboho fikun pe awọn ara Eko ti n foju sọna lati gbalejo ikọ Yoruba Nation lọjọ Satide, ti iwọde naa yoo si lọ wọọrọ wọ.
Wayi, Sunday Igboho ti wa rawọ ẹbẹ si ileesẹ ọlọpa nipinlẹ Eko lati pese eto aabo to peye fawọn oluwọde naa nitori gbogbo ọmọ Yoruba lo n fẹ ki iwọde naa waye.



















