Dejo Tunfulu: Àwọn òṣèré tíátà bẹ̀rẹ̀ kíkọ́ ilé sórí ilẹ̀ gbajúgbajà adẹ́rìnínpòṣónú tó papò dà

Dejo Tunfulu

Oríṣun àwòrán, dejo Tunfulu/laideolabanji

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Yorùbá ní dídùn dídùn báyìí ni ìrántí olódodo.

Àwọn òṣèré tíátà ti bẹ̀rẹ̀ sí ní kọ ilé sí orí ilẹ̀ gbajúgbajà òṣèré adẹ́rìnínpòṣónú, Adekunle Adetokunbo tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ mọ̀ sí Dejo Tunfulu tó di olóògbé láìpẹ́ yìí.

Ní ọjọ́ kìíní, oṣù kẹrin, ọdún 2022 ni Dejo Tunfulu dágbére fáyé lẹ́ni àádọ́ta ọdún lẹ́yìn àìsàn ráńpẹ́.

Àkọlé fídíò, 'Fásitì Nàìjíríà kò gbà mi wọlé ló mú mi sá lọ Ukraine, àmọ́ ohun tí ojú mi rí nínú ogun náà rèé kí ń tó sá wá Nàìjíríà'

Ní orí ilẹ̀ olóògbé náà ni wọ́n sin-ín sí ní ìlànà ẹ̀sìn Islam.

Gbajúgbajà òṣèré kan, Olaide Olabanji ti wá fi fọ́nrán kan léde báyìí léyìí tó ń ṣe àfihàn orí ilẹ̀ olóògbé níbi tí wọ́n sin Dejo Tunfulu sí.

Ní orí ayélujára Instagram Olaide Olabanji ni ó fi fọ́nrán fídíò tó ṣàfihàn pé iṣẹ́ ilé kíkọ́ náà tí bẹ̀rẹ̀ sí.

Ohun tí Olabanji kọ sí abẹ́ fọ́nrán náà ni wí pé "iṣẹ́ dáadáa ṣì ń tẹ̀síwájú, lónìí ní orí ilẹ̀ Dejo Tunfulu, iṣẹ́ ti bẹ̀rẹ̀, kí Ọlọ́run tẹ sí afẹ́fẹ́ rere."

Skip Instagram post
Allow Instagram content?

This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of Instagram post

Àkọlé fídíò, Bí mo ṣe rí ọ̀pọ̀ Mílíọ̀nù Nàírà tí mo sì dáà padà fún Ọlọ́pàá lọ́dún 1971 àmọ́ ǹkan t'íjọba sọ rèé - Baba Shonubi

Ohun tí a rí nínú fídíò náà ni wí pé iṣẹ́ ilé kíkọ́ ti bẹ̀rẹ̀ níbẹ̀ tí ìròyìn náà sì ti ń fa kí àwọn olólùfẹ́ olóògbé Dejo Tunfulu máa kan ṣáá sí àwọn tó dìde ìrànwọ́ náà.

Lẹ́yìn tí Dejo Tunfulu jáde láyé tí àwọn ènìyàn sì gbọ́ wí pé gbajúgbajà òṣèré adẹ́rìnínpòṣónú náà kò ní ilé ti ara rẹ̀ wí pé ó ń yá ilé gbé ni àwọn ènìyàn ti ń kùn wí pé pẹ̀lú gbogbo bí ó ṣe fara ṣiṣẹ́ nídìí tíátà tó, kò yẹ kó jẹ́ pé irú Dejo Tunfulu ni kò ní nílé lórí.

Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ní ilẹ̀ tó ti rà kalẹ̀ ní orúkọ ara rẹ̀ kí ọlọ́jọ́ tó dé.

Àkọlé fídíò, Wọ́n jí pè mi láàrọ̀ pé ọmọ mi bímọ, ó dákú àmọ́ bí mo ṣe débẹ̀, àt'òkú ọmọ mi, àt'òkú

Àwọn olólùfẹ́ Dejo Tunfulu fi ìdùnnú hàn sí bí ilé kíkọ́ ṣe bẹ̀rẹ̀ lórí ilẹ̀ rẹ̀

Àwọn olólùfẹ́ gbajúgbajà òṣèré adẹ́rìnínpòṣónú, Dejo Tunfulu ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìdùnnú wọn hàn lórí Fọ́nrán tí Olabanji fi léde.

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ló ń sọ̀rọ̀ ìwúrí tí wọ́n sì ń fi àdúrà ránṣẹ́ sì àwọn tó wà nídìí ilé kíkọ́ náà.

Bákan náà ni wọ́n gbàdúrà pé kí Ọlọ́run fún wọn ní oore ọ̀fẹ́ láti parí iṣẹ́ rere tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ọ̀hún.

Àkọlé fídíò, Bí mo ṣe rí ọ̀pọ̀ Mílíọ̀nù Nàírà tí mo sì dáà padà fún Ọlọ́pàá lọ́dún 1971 àmọ́ ǹkan t'íjọba sọ rèé - Baba Shonubi