Chrisland Pupil Sexual Scandal: Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ wa kìí ṣe àṣemáṣe

Chrisland School

Oríṣun àwòrán, Chrisland School

Ilé iṣẹ́ Ọlọ́pàá Ìpínlẹ̀ Èkó tí ránṣẹ́ pé gbogbo àwọn tó lọ́wọ́ nínú ẹ̀sùn ìbálòpọ̀ ọmọdé èyí tí wọ́n fi kan àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé ẹ̀kọ́ Chrisland tó wà ní agbègbè Victoria Garden City, ìpínlẹ̀ Eko.

Agbẹnusọ ilé iṣẹ́ Ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Eko, Benjamin Hundeyin sọ fún àwọn akọ̀ròyìn ní ọjọ́ ìṣẹ́gun, ọjọ́ kọkàndínlógún, oṣù kẹrin, ọdún 2022 wí pé gbogbo àwọn tí ọ̀rọ̀ ẹ̀sùn ìbálòpọ̀ ọmọ ọdún mẹ́wàá, tó jẹ́ akẹ́kọ̀ọ́ ìwé kẹfà ni ilé ẹ̀kọ́ Chrisland ní àwọn tí darí láti lọ wí tẹnu wọn ní ẹ̀ka to ń mójútó ìwà ọ̀daràn tó wà ní Panti.

Nígbà tó ń sọ ibi tí ìwádìí dé dúró lórí ọ̀rọ̀ náà, Hundeyin ní àwọn ti ní kí àwọn tí ọ̀rọ̀ náà kan kọ gbogbo ohun tí wọ́n bá mọ̀ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún.

Bákan náà ló ní lẹ́yìn èyí ni ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò yóò bẹ̀rẹ̀ ní pẹrẹu.

Ó ṣàlàyé pé lára àwọn tí ọ̀rọ̀ náà kan ni olùkọ́ àgbà ilé ẹ̀kọ́ Chrisland, G. I. Azike àti àwọn òbí akẹ́kọ̀ọ́ tí wọ́n fi ẹ̀sùn kàn wí pé wọ́n ṣe àṣemáṣe pẹ̀lú ọmọ àwon lásìkò tí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé ẹ̀kọ́ ọ̀hún lọ kópa níbi ètò eré ìdárayá àwọn ilé ẹ̀kọ́ káàkiri àgbáyé.

Ní ìlú Dubai, orílẹ̀ èdè United Arab Emirates ní ìdíje náà ti wáyé nínú oṣù kẹta ọdún 2022.

Àkọlé fídíò, Bí mo ṣe rí ọ̀pọ̀ Mílíọ̀nù Nàírà tí mo sì dáà padà fún Ọlọ́pàá lọ́dún 1971 àmọ́ ǹkan t'íjọba sọ rèé - Baba Shonubi

Kí ló ti ṣẹlẹ̀ sẹ́yìn?

Ní ọjọ́ Ajé, ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù kẹrin ni ìyá akẹ́kọ̀ọ́ náà fi fọ́nrán kan léde níbi tó ti fẹ̀sùn kan àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé ẹ̀kọ́ Chrisland kan wí pé wọ́n fún ọmọ òun ní oògùn olóró mú, tí wọ́n sì fi ipá bá lòpọ̀.

Fọ́nrán ọ̀hún sì ti ń fà awuyewuye láàárín àwọn ènìyàn lórí ayélujára.

Ìjọba Ìpínlẹ̀ Èkó náà sì ti gbé ilé ẹ̀kọ́ náà tì pa fún ìgbà díẹ̀ náà nítorí ẹ̀sùn náà.

Kí ni ilé ẹ̀kọ́ Chrisland sọ?

Nínú àtẹ̀jáde kan tí Akin Fadeyi, ọkàn lára àwọn ìgbìmọ̀ Aláṣẹ ilé ẹ̀kọ́ Chrisland fi síta lórúkọ ilé ẹ̀kọ́ náà sọ wí pé lóòótọ́ ni akẹ́kọ̀ọ́ náà wà lára akẹ́kọ̀ọ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́rin tí àwọn kó lọ sí ìlú Dubai láti kópa níbi eré ìdárayá nínú oṣù kẹta ọdún yìí.

Àkọlé fídíò, Wọ́n jí pè mi láàrọ̀ pé ọmọ mi bímọ, ó dákú àmọ́ bí mo ṣe débẹ̀, àt'òkú ọmọ mi, àt'òkú

Fadeyi ni ẹ̀sùn ìfipábánilòpọ̀ tí ìyá ọmọ náà fi kan àwọn akẹ́kọ̀ọ́ náà kìí se òtítọ́.

Ó ṣàlàyé pé àwọn akẹ́kọ̀ọ́ márùn-ún nínú gbogbo àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tí àwọn kó lọ sí Dubai àti wí pé ọmọbìnrin náà lọ ṣáájú ìwà àṣemáṣe ọ̀hún.

Ó fi kún wí pé àwọn akẹ́kọ̀ọ́ náà kópa nínú ìdíje "Truth or Dare" lẹ́yìn tí àwọn tí àwọn ti paná pé kí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ náà lọ sùn.

Ó ní èyí ló ṣokùnfà ìdí tí àwọn fi ní kí akẹ́kọ̀ọ́ náà lọ rọ́kún nílé fún ìgbà kan ná.

Àkọlé fídíò, FUTA First Class Twins