Okùnrin kan ra àpò ìrẹsì mẹjì, ó fi ọ̀dọ́kùnrin méjì ṣe onídùró nílùú Eko

Bags of rice

Oríṣun àwòrán, Armiyau Shuaibu

Obinri kan ti wọnu oko gbese lẹyin ti okunrin kan ra irẹsi ninu ṣọọbu rẹ lai san owo fun, ṣugbọn to fi awọn ọmọkunrin meji silẹ ni ṣọọbu ọhun dipo owo.

Gẹgẹ bii ohun ti a gbọ, Ọjọbọ ni okunrin naa wọ inu ṣọọbu Olabisi Opeyemi to wa ladugbo Felicia Oke, lagbegbe Olowora niluu Eko.

Nibẹ lo si ti sọ pe oun fẹ ra apo irẹsi meji, toun ti awọn ọdọkunrin meji ti iye ọjọ ori wọn ko ju ọdun marundinlogun lọ.

Aburo Opeyemi, Alima, to wa ninu ṣọọbu ọhun lasiko naa ta irẹsi fun okunrin naa pẹlu igbagbọ pe aburo rẹ ni awọn ọdọkunrin meji ọhun.

Lẹyin ti okunrin naa ra apo irẹsi meji ọhun, o fi awọn ọdọkunrin meji naa silẹ si ṣọọbu naa, o si sọ fun Alima pe oun n bọ wa lati lọ gba owo nitosi.

Ṣugbọn lẹyin iṣẹju diẹ ti okunrin naa ko tete de ni ọkan lara awọn ọdọkunrin to fi silẹ sọ pe oun fẹ lọ ṣawari rẹ.

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Asa: Ọ̀rọ̀ Asopò ni á ń gbéyẹ̀wò pẹ̀lú Arabìnrin Tope Atoyebi láti Ilorin

Ko pẹ si asiko naa ni ọdọkunrin keji naa tu sọ pe oun fẹ maa lọ ṣugbọn Alima kọ jalẹ pe ayafi ti okunrin to ko awọn mejeji wa ba pada wa, ṣugbọn ọdọkunrin naa ni oun ko mọ okunrin naa ri.

Àkọlé fídíò, Sen Francis Fadahunsi sọ ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lórí kíkó ẹ̀rù wọlé láti ẹnubodè Nàìjíríà báyìí

Ọdọkunrin ọhun sọ pe ni ṣe okunrin naa pade lẹba ọna to si bẹ oun lati ran an lọwọ lati gbe irẹsi ninu ṣọọbu Alima.

Asiko yii lo ti han gbangba si Alima pe onijibiti ni okunrin ọhun, ati pe o ti fẹsẹ fẹ.

Àkọlé fídíò, Ẹni tó bá ni kí n fi iṣẹ́ kòkò mímọ sílẹ̀, mi ò lè fẹ́ẹ láéláé - Adekemi Àgùnbánirọ̀

Nigba to n ba awọn akọroyin sọrọ, ẹgbọn Alima to ni ṣọọbu naa, Opeyemi sọ pe gbese nla ni iṣẹlẹ naa da si oun lọrun.

O ni oun ko fi ọrọ naa to ileeṣẹ ọlọpaa leti nitori ẹni mimọ ni ọkan lara awọn ọdọkunrin naa jẹ si oun ni adugbo

Àkọlé fídíò, Ṣé ìwọ mọ̀ pé Olodumare lè lo Aje láti gbé ẹ lọ síbi ire?- Abiodun Fatomilola

O ṣalaye pe "Mi o si ni ṣọọbu lasiko ti iṣẹlẹe naa waye nitori mo wa lori idubulẹ aisan, ṣugbọn lẹyin wakati diẹ ti okunrin naa ra ọja tan ni mo to mọ pe wọn ti lu aburo mi ni jibiti."

"Iṣẹlẹ naa da omi tutu si mi lọkan nitori gbese nla lo da silẹ fun mi."

Àkọlé fídíò, Adeyemi Olubunmi Crown: Láti ìgbà ti mo ti fún ọkọ mi ni ẹ̀bùn mọ́tò ni ìfẹ́ wa ti yàtọ̀

Ẹwẹ, awọn eeyan kan ni adubo ti iṣẹlẹ naa ti waye ti sọ pe o ṣeeṣe ko jẹ pe ṣe ni okunrin to ra irẹsi ọhun fi oogun ba Alima sọrọ.

Titi di akoko ti an ko iroyin yii jọ, wọn ko tii foju ganni okunrin ọhun, ko si si ẹni to le sọ ibi to ti wa.