Malaria Vaccine: Àjọ WHO gbé abẹ́rẹ́ àjẹsára àìsàn ibà jáde fún ilẹ̀ Afrika

mosquito.

Oríṣun àwòrán, Science Photo Library

Ajọ eleto ilẹra lagbaye, WHO ti sapejuwe abẹrẹ ajẹsara tuntun ti wọn gbe jade fun aisan iba pe ohun ṣiṣẹ tako arun naa ni agọ ara.

Ajọ WHO gbe abẹrẹ ajẹsara naa jade lẹyin ti ileeṣẹ apoogun GSK lo fun awọn eniyan ni awọn orilẹede mẹta.

Lasiko ti wọn n ṣe aṣẹwo abẹrẹ ajẹsara naa ni Malawi, Ghana ati Kenya ni wọn ri pe lọna ida ogoji ti abẹrẹ ajẹsara naa fi koju arun iba.

O kere tan ẹgbẹrun lọna irinwo eniyan ni aisan iba n pa ni ọdọọdun, ti ida awọn to n lugbadi aisan naa si jẹ ọmọde ti ko i tii pe ọdun marun un ni ilẹ Afrika.

Àkọlé fídíò, Adeyemi Olubunmi Crown: Láti ìgbà ti mo ti fún ọkọ mi ni ẹ̀bùn mọ́tò ni ìfẹ́ wa ti yàtọ̀

Adari Ajọ WHO, Tedros Ghebreyesus sapejuwe abẹrẹ ajẹsara naa gẹgẹ bi aṣeyọri nla fun awọn eniyan ni ilẹ Afrika ati ni agbaye pẹlu.

O ti lẹ ni ẹgbẹrun ọdun ti wọn ti n gbiyanju lati ṣe abẹrẹ ajẹsara ti yoo koju aisan iba lai si aṣeyọri kankan lori rẹ.

Aisan Iba

Oríṣun àwòrán, BRIAN ONGORO

Nibayii ti wọn ti sẹ aṣeyori lori abẹrẹ ajẹsara naa, eleyii jẹ iṣẹ nla fun awọn oniṣegun oyinbo ati apoogun kaakiri agbaye.

Àkọlé fídíò, Samuel Oluwafemi sọ bí Covid 19 ṣe bí ìdíje oníjó àti eré fún àwọn Odi àti Adití sí rere

Abẹrẹ ajẹsara naa ti wọn pe orukọ rẹ ni RTS,S - ti ṣiṣẹ lati gbogun ti aisan iba fun ọdun mẹfa ki wọn to fi ọwọ rẹ soya bii abẹrẹ ajẹsara to lamilaaka.

Àkọlé fídíò, Ebun Oloyede Olaiya Igwe sọ ohun tí ojú rẹ̀ rí lásìkò àìsàn kídìnrín tó yọ ọ́ lẹ́nu

Ajo WHO ni eleyii yoo doola ẹmi ẹgbẹgbẹrun awọn ọmọde kaakiri agbaye ati ilẹ Afrika ti aisan iba ti n ba wọn finra julọ.

Àkọlé fídíò, Africa Eye wádii àwọn tó wà nídìí ìgbésùmọ̀mí ni Mozambique

Aisan iba apaniyan

Aisan iba jẹ ọkan lara awọn aisan to n da sẹli ẹjẹ,blood cells ru lẹyin ti ẹfọn ba ti jẹ eniyan.

Awọn oogun to n gbogun ti aisan iba yii ati awọn oogun ẹfọn ti mu ki aisan iba dinku laarin awọn eniyan.

mosquito-net.

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Ọpọlọpọ awọn eniyan ni ilẹ Afrika ni wọn n fi ara gba ninu ijamba aisan iba nitori o kere tan ọmọde to to 260,000 ni aisan iba naa mu ẹmi wọn lọ ni ọdun 2019.

Àkọlé fídíò, Adepoju Abdulsalamm ẹni ọdun 18 tó n fi kẹ̀kẹ́ dára fi kiri ẹja tó fi n tà wàràwàrà