Ẹgbẹ́ APC ní láti wà lórí oyè kí ìjọba tiwantiwan lè fẹsẹ̀ múlẹ̀ dáadáa - Mai Mala Buni

Buni

Oríṣun àwòrán, @GarantiBrah

Alaga ẹgbẹ oṣẹlu APC, to tun jẹ gomina ipinlẹ Yobe, Mai Mala Buni ti sọ pe afojusun ẹgbẹ ọhun ni lati tukọ ijọba Naijiria fun ọdun mejilelọgbọn.

Mai Mala lo sọ ọrọ naa lasiko to n yan igbimọ ẹlẹni mọkanlelọgọta kan ti yoo ṣeto apero ẹgbẹ ọhun to n bọ lọna ni ọọfisi ẹgbẹ naa to wa niluu Abuja.

Gẹgẹ bo ṣe sọ, ẹgbẹ eṣelu APC ni lati wa lori ipo fun ọpọ ọdun ki ijọba tiwantiwa to ti bẹrẹ lati ọdun 2015 le fẹsẹ mulẹ daadaa.

O ṣalaye pe awọn gbe igbimọ naa kalẹ ki wọn le mu ipinu naa ṣẹ.

Buni

Oríṣun àwòrán, @BashirAhmaad

Lara awọn to wa ninu igbimọ ọhun ni awọn gomina, minisita, ṣenatọ atawọn agbagba oloṣelu, eyii ti gomina ipinlẹ Jigawa, Muhammadu Badaru Abubakar ṣe olori wọn.

Lati igba ti wọn ti yan gomina ipinlẹ Yobe yii gẹgẹ bii alaga fidihẹ ẹgbẹ APC ni awọn awuyewuye kan ti n waye ninu ẹgbẹ naa.

Ṣugbọn o ti n gbiyanju lati ri daju irẹpọ wa ninu ẹgbẹ ọhun.

Àkọlé fídíò, Àwọn ọ̀rọ̀ Yorùbá kan wà tí ẹ kò lè lò pọ̀ mọ́ ara wọn, àwn ọ̀rọ̀ tẹ́ẹ lè fi rọ́pò rèé