Lauretta Onochie: Àwọn ará ìlú lẹ́tọ̀ọ́ lábẹ̀ òfin láti fi ẹjọ́ ẹni tó ń náwó yàlàyòlò sun agbófinró

Oríṣun àwòrán, Okan Caliskan
Agbẹjọro kan, Jiti Ogunye, ti sọ pe ko buru ki eeyan maa na owo yalayala labẹ ofin, ṣugbọn ijọba le ṣe iwadii owo naa ti wọn ba fi ẹjọ irufẹ ẹni bẹẹ sun pe idi owo rẹ ko mọ.
Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ, Ogunye sọ pe awọn agbofinro kii ṣe arinurode olumọran ọkan ti yoo mọ ẹni to n ṣe jibiti lai si iranlọwọ awọn ara ilu.
Gẹgẹ bo ṣe, "ofin ko sọ pe ki eeyan má na owo tí kò pa, ohun ti ofin sọ ni pe ki eeyan ma fi ọna ẹru pa owo tabi ko jokoo sibi kan lati ma na owo to ji.
- Sùkẹ̀! Ọ̀rọ̀ òṣèlú ni gbogbo ẹ tí Akeredolu ṣe tako ìdásílẹ̀ Oduduwa Nation - Banji Akintoye
- Bí òkú ṣe máa ń bàjẹ́ ní Mọ́ṣúárì tẹ́ẹ ò bá san owó ìtọ́jú fáwọn olùtọ́jú òkú rèé
- Wo àwọn ọ̀rọ̀ tó ki pọ́pọ́ tí Lateef Adedimeji fi kọrin ọjọ́ ìbí 23 fún Adebimpe Oyebade "Onítèmi"
- Ẹ̀yà Yorùbá ti fara ṣiṣẹ́ púpọ̀ fún Naijiria, nítorí nàá à kò le déèdé sọ pé a fẹ́ kúrò - Àgbààgbà Yorùbá
O ṣalaye pe "ti eeyan ba n na owo yala-yolo, ti awọn agbofinro si ṣe iwadii, ti wọn si ka ẹṣẹ mọ irufẹ ẹni bẹẹ lọwọ, nigba yẹn ni ẹni naa da ẹṣẹ labẹ ofin."
"Ṣugbọn a ko le sọ pe eeyan ti ṣẹ si ofin nitori o n nawo yala."

Oríṣun àwòrán, succo
Ṣaaju ni amugbalẹgbẹ Aarẹ Muhammadu Buhari, Lauretta Onochie ti kọkọ sọ loju opo Twitter rẹ pe gbogbo awọn to n gbe igbe aye ti apo iṣuna wọn ko ka le kawọn pọn ro ẹjọ niwaju adajọ.
Lauretta ni "O ti pẹ ti mo ti n reti ki Naijiria ni iru ofin yii to wa nilẹ Gẹẹsi, eyii to faye gba awọn eeyan lati fi ẹjọ ẹni to n na inakuna, ti ko si ni ọna kan pato ti owo ti n wọle, sun ijọba.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Amubalẹgbẹ Aarẹ ọhun sọ pe inu oun dun pe ajọ to n ṣewadii iwa jẹgudujẹra, ICPC, ti ba ọrọ naa de ile to ga julọ ni Naijiria.
- A ò pe Sunday Igboho lọ́mọ alè Yorùbá o àmọ́, a ó jọ́ bèrè lọ́wọ́ Alálẹ̀ Ibadan àti gbogbo Yorùbá ni - Olubadan
- Mo gbàdúrà kí n má kábàmọ́ fífagilé ẹjọ́ pẹ̀lú àwọn tó jí àwọn ìbejì mi gbé nílé ẹjọ́ - Akeugbagold
- Agbébọn yabo ílé ìtajà ìgbàlódé, èèyàn mẹ́wàá bá d'èrò ọ̀run
- Bàbá ni Alake Ẹgba jẹ́ fún mi, mi ò lè ṣe ìkọlù sí ààfin rẹ̀ - Igboho
Nigba ti agbẹjọro Ogunye n fesi si ọrọ Lauretta, o ni kii ṣe ile ẹjọ to ga julọ ni Naijiria lo n ṣe ofin, bi ko ṣe awọn ile igbimọ aṣofin ijọba apapọ, ati ti ijọba ipinlẹ.
O pari ọrọ rẹ pe, ko tii si ofin kankan ni Naijiria to sọ pe ara ilu ko le na owo bo ṣe wuu labẹ ofin.
"Ṣugbọn ara ilu lẹtọọ labẹ ofin lati fi ẹjọ irufẹ ẹni bẹẹ sun awọn agbofinro, bo ti tilẹ jẹ pe inakuna kii ṣe ẹṣẹ labẹ ofin."
- 'Ohun táá ṣe rèé bẹ́ẹ bá kọ̀ láti wá gbé àwọn òkú yín kúrò ní Mọ́ṣúárì wa'
- Ọwọ́ tẹ afurasí ọ̀daràn Fulani tó ṣe ìkọlù sílé ìyá Sunday Ighoho
- Àwọn ọ̀dọ́ Ibarapa yabo ọọ́físì Seyi Makinde lórí ètò àbò tó mẹ́hẹ
- Ṣọ́ra fún ètò àwọn Darandaran, àwọn ọmọ Ekiti nílẹ̀ òkèèrè kìlọ̀ fún Fayemi
- Àwọn ajínigbé tún ti pé wá lóni ṣùgbọ́n a kò ti rí ìyè owó tí wọn ní ká mu wá-Olori Oba Imope














