Ibarapa: Àwọn ọ̀dọ́ ṣe ìwọ́de lọọọ́físì Seyi Makinde lẹ́yìn tí ọlọ́pàá ti àwọn ọmọ ẹgbẹ́ OPC tó mú Wakili mọ́lé

Awọn ọdọ kan ti ya bo ọọfisi ijọba ipinlẹ Oyo to wa ni Agodi, niluu Ibadan, lati fi aidunu wọn lede nitori ipaniyan to n waye nipinlẹ ọhun, paapaa lagbegbe Ibarapa, Oke-Ogun atawọn agbegbe miran.
Bẹẹ ni awọn ọdọ ọhun tun n ṣefẹhonuhan lodi si bi ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Oyo ṣe ti awọn ọmọ ẹgbẹ OPC mẹta kan mọle lẹyin ti ile ẹjọ kan paṣẹ pe ki wọn ṣe bẹẹ.
Awọn ọmọ ẹgbẹ OPC naa wa lara awọn ikọ to fi panpẹ ọba mu Iskilu Wakili, ti wọn fẹsun kan pe o n ṣagbatẹru ijinigbe ati ipaniyan niluu Ibarapa.
- Ọwọ́ tẹ afurasí ọ̀daràn Fulani tó ṣe ìkọlù sílé ìyá Sunday Ighoho
- Mo gbàdúrà kí n má kábàmọ́ fífagilé ẹjọ́ pẹ̀lú àwọn tó jí àwọn ìbejì mi gbé nílé ẹjọ́ - Akeugbagold
- 'Ẹ wá gbé àwọn òkú yín o! A ò ráyè kó òkú sí mọ́, bí bẹ́ẹ̀ kọ́... - Aláṣẹ Mọ́ṣúárì Ilorin
- 'Ìjọba Kwara kàn fẹ́ fi ọ̀rọ̀ Hijab dá ìjà sílẹ̀ láàrin Krìstíẹ́ní àti Mùsùlùmí ni'
Ṣaaju ni ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Oyo ti kọkọ ti awọn ọmọ ẹgbẹ OPC naa mọle, ti wọn si fi ẹsun ipaniyan ati didana sun dukia lọna aitọ kan wọn, ki wọn to ni ki wọn logba diẹ ninu ọgba ẹwọn ki iwadii le tẹsiwaju.

Awọn olufẹhonuhan ọhun, ti ọpọ ninu wọn wa lati Ibarapa ya bo ọọfii ijọba ọhun, ti wọn si n kọrin pe ko si abo kankan fun awọn eeyan awọn pẹlu oriṣiriṣi akọle lọwọ.
Ọkan lara awọn to ṣagbatẹru iwọde na, Oladiran Oladokun sọ fun awọn akọrọrin pe bi awọn ọlọpaa ṣe ti awọn ọmọ ẹgbẹ OPC naa mọle n ṣafihan pe awọn ọlọpaa ko nilo iranlọwọ awọn eeyan ilu lati mu awọn ọdaran lawujọ.
Oladokun ṣalaye pe Wakili da awọn eyan Ibarapa laamu pupọ, bo tilẹ jẹ pe awọn ọlọpaa kọ lati mu, awọn ọlọpaa ọhun tun n fiya jẹ awọn ọmọ ẹgbẹ OPC to mu afurasi naa.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, "a wa nibi lati ṣe ifẹhonuhan lodi si bi awọn awọn agbofinro ṣe mu awọn ọmọ ẹgbẹ OPC mẹta to mu Wakili to n da agbegbe Kajola, Ayete atawọn agbegbe miran laamu,ti wọn si tun ti wọn mọle."
"Won Ṣawari Wakili, wọn si fi panpẹ ofin mu, ṣugbọn awọn ọlọpaa ti wọn mọle, eyii jẹ ohun to buru jai, to tun n ṣafihan fun awọn eeyan ilu pe ko yẹ ki wọn maa ran ileeṣẹ ọlọpaa lọwọ lati mu awọn ọdaran."
- Omi Àgbọn, Ọsàn wẹ́wẹ́, ìbẹ́pẹ àtàwọn ohun mẹ́rin mìí tóo gbọ́dọ̀ mu lásìkò ẹ̀run rèé
- Ṣọ́ra fún ètò àwọn Darandaran, àwọn ọmọ Ekiti nílẹ̀ òkèèrè kìlọ̀ fún Fayemi
- Ẹ̀yìn taa ni Alake ti Egba tò sí lórí ọ̀rọ̀ Oduduwa Nation tí Sunday Igboho sọ?
- Kò sí Oduduwa Nation kankan ni ilẹ̀ Iwo! Kí n má gbọ́ ọ - Oluwo
- Ǹkan pàtàkì márùn-ún tí gbogbo obìnrin tó ní ojú ara gbọ́dọ̀ mọ̀
- ''Ẹ ó ríjà Ọba, tí ẹ bá gbìyànjú láti fọ́wọ́ kan Sunday Igboho''














