Iléeṣẹ́ aṣọ́bodè gbẹ́sẹ̀lé ‘Container’ tó kún fún ìbọn nílùú Eko

Oríṣun àwòrán, Anambra specials
Ileeṣẹ aṣobode Naijiria ti gbẹsẹle ile ẹru kan ti wọn ba ibọn atawọn ohun ija oloro mii ninu rẹ lagbegbe Tin Can Island, niluu Eko.
Wọn ṣawari ile ẹru ọhun lasiko ti wọn n ṣe ọkan lara awọn ayẹwo ti wọn maa n ṣe nileeṣẹ naa.
Agbẹnusọ ileeṣẹ aṣobode ni Tin Can Island, Uche Ejesieme lo fidi ọrọ naa mulẹ fun awọn akọroyin.
- Wo ààrẹ orílẹ̀-èdè tó ṣiṣẹ́ awakọ̀ "taxi" kó tó di ààrẹ
- Àwọn ọlọ́pàá ti gbé tọkọtaya tí wọ́n fi ẹ̀sùn kàn pé ó fi ọmọ oṣù mẹ́fà dí gbèsè tó fi kú
- Ó ti ṣe díẹ̀ tí mo ti ń gbé pẹ̀lú ìbànújẹ́, ayé ti sú mi - Ibrahim Chatta
- Àwọn ọlọ́pàá gbé òkú Sylvester Oromoni, akẹ́kọ̀ọ́ Dowen College to ku l'Eko fún àwọn òbí rẹ̀ lẹ́yìn àyẹ̀wò 'Autopsy'
- Ìyàwó Timothy Adedoge ké gbàjarè lórí èsì àyẹ̀wò ikú tó pa ọkọ rẹ̀
- Ọkọ mi ti ń sọ tẹ́lẹ̀ pé òun yóò pa ara òun, àmọ́ ẹbí kò ka ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí - Ìyàwó ọkùnrin tó bẹ́ sí odò ọ̀sà
- Wo àwòrán ayẹyẹ ìgbéyàwó láàrín Lateef Adedimeji àti Adebimpe Oyebade
- 'Mi ò rí ọkùnrin bá lòpọ̀ fún ọdún kan gbáko lásìkò "lockdown" àmọ́ mo dán ǹkan wò'
- Àjò kò lè dùn títí... Mò ń padà sí oko lẹ́yìn sáà ìjọba mi - Buhari
O ni awọn ṣawari ile ẹru ọhun lasiko ọkan lara awọn ayẹwo ti wọn maa ṣe.
"Lẹyin ti a ṣawari rẹ ni ni a paṣẹ ki wọn gbe ile ẹru naa lọ si ọọfisi wa fun ayẹwo ni kikun ati iwadii to peye."
O fi kun pe ọpọ ohun ni awọn ko tii mọ nipa bi ile ẹru naa ṣe jẹ ṣugbọn awọn ko ni fi ohunkohun pamọ fun awọn akọroyin lori iwadii awọn.
Iṣẹlẹ yii lo n waye lẹyin ti ọga agba ileeṣẹ ọlọpaa, Usman Baba ke si awọn agbofinro lati jawe sobi iṣẹ wọn ni imurasilẹ ọdun 2022 to n bọ lọna.
Usman Baba sọ pe ọdun to ni apẹrẹ ni ọdun 2022 yoo jẹ nitori ọdun naa ni yoo ṣaaju ọdun 2023 ti eto idibi Aarẹ yoo waye.
Ẹwẹ, iroyin ni ẹni to ni ile eru naa ti kọkọ sọ ṣaaju pe ẹrọ tẹlifiṣọn agbelewo lo wa ninu rẹ ki akara to tu sepo.














