Aishat Adesina: Àwa akẹ́ẹ̀kọ́ lòdì sí bí àwọn adarí iléẹ̀kọ́ OAU ṣe ti fásitì, ìfẹ̀hónúhàn tẹ̀síwújú lórí ikú akẹ́ẹ̀kọ́

Oríṣun àwòrán, OTHERS
Ẹgbẹ awọn akẹkọọ ni Fasiti Ọbafemi Awolowo ,NANS ti tako aṣẹ adari ileẹkọ naa pe ki awọn akẹkọọ kuro ni ileewe naa ni kiakia.
Ẹgbẹ awọn akẹkọọ ọhun ninu atẹjade ti wọn fi lede ṣe apejuwe aṣẹ fasiti naa gẹgẹ bi ohun to lodi si ẹtọ awọn akẹkọọ.
Awọn alaṣẹ fasiti naa lo paṣẹ ọhun lẹyin ti awọn akẹkọ bẹrẹ ifẹhọnu nitori ọkan lara wọn Aishat Adesina to gbẹmi mi lasiko to n ṣe aisan, ti wọn si gbe e lọ si ileewosan to wa ninu ọgba fasiti naa.
Ninu ọrọ ti wọn sọ, awọn akẹkọọ faraya nitori pe wọn da ẹbi iku akẹkọọbinrin naa ru ileewosan fasiti OAU nitori aibikita wọn ni eto ilera akẹkọọ naa nigba to lọ si ileewosan ọhun fun iwosan.
''Awọn oṣiṣẹ ileewosan fasiti naa ko dahun si obinrin ọhun to n ṣe aisan, ti wọn si fi silẹ titi ti ẹmi fi bọ ni ara rẹ.''
''Lẹyin naa ni wọn paṣẹ pe ki wọn gbe e lọ si ileewosan Adventist to wa ni igboro, amọ ileewosan naa ni akẹkọbinrin naa ti ku ki wọn to gbe e de ibẹ''.

''Ẹtọ wa ni lati fi ẹhonuhan, amọ kaka ki awọn alaṣẹ ba wa sọrọ nigba ti a kesi wọn, niṣe ni wọn kọ iwe si awọn akẹkọọ lati fi ọgba silẹ''
''A ko ni ibi kankan lọ nitori awọn akẹkọọ n kọ idanwo wọn lọwọ, nitori naa ki awọn alaṣẹ da ero wọn pada.''
- Ẹ fún wa ní ààrẹ tó pegede láì náání ẹkùn tó ti wa - Lamido Sanusi
- Nǹkan ṣẹlẹ̀ l'Abuja, Ondo àti Eko lọ́jọ́ Òmìnira
- Wo okùnfà ìṣubú ìjọba alágbádá àkọ́kọ́ àti ẹ̀kọ́ fun olóṣèlú òde òní
- Ǹkan tí wọ́n kọ fún Buhari ló kà, Sunday Igboho kò ṣẹ̀ s'ófin- Ilana Omo Oduduwa
- Ọmọ ìkókó yìí bẹ̀rẹ̀ ǹkan oṣù l'ọ́mọ oṣù mẹ́rin, ó tún kojú àìsàn jẹjẹrẹ ilé ọmọ
Ẹgbẹ awọn olukọ naa wa kesi awọn akẹkọọ lati tẹsiwaju ifẹhonuhan to n waye naa paapaa ni iwaju ileẹkọ naa lati tako aṣẹ adari fasiti naa.
Bakan naa ni wọn paṣẹ ki awọn alaṣẹ ileewe naa ṣi ileewe pada fun awọn akẹkọọ lati pari idanwo ti wọn n ṣe lọwọ.















