Nigeria Independence Day: Gbọ́ bí àwọn èèyàn ṣe ń ka ẹ̀jẹ́ Nàìjíríà
Se iwọ le ka orin ogo ilẹ wa gangan?
Àsía aláwọ̀ ewéko àti funfun, orin ògó ilẹ̀ wa àti ẹ̀jẹ́ orilẹ-ede wà lára àwọn àmì ìdánimọ̀ ọmọ Naijiria.
Lọdun 1960 ninu oṣu kẹwaa ni Naijiria gba ominira kuro lọwọ ijọba amunisin ti ilẹ Gẹẹsi Ǹ jẹ́ o mọ àwọn èèyaǹ wọ̀nyí tó jà fún òmìnira Nàìjíríà?.
Àsía aláwọ̀ ewé àti funfun, orin ògó ilẹ̀ wa àti ẹ̀jẹ́ orilẹ-ede wà lára àwọn àmì ìdánimọ̀ ọmọ Naijiria.
- Aṣírí tú! A ti mọ àwọn tó ń ṣagbátẹrù Sunday Igboho àti Nnamdi Kanu nínú ìjọba - Buhari
- 'Tí ìjọba tó wà ṣáájú Buhari bá ṣe é dára ni, kò ni rọrùn fún Buhari láti gba ipò náà, ẹ fi ara yín sípò Buhari'
- Ilé ẹjọ́ ju Àfáà tó ń gbé àwọ̀ Femi Adesina wọ̀ sí ẹ̀wọ̀n ọdún 28, ó tún pàdánù dúkìá
- Nàìjíríà kàn takú ni, ẹ ò páàsì, ẹ ò féèlì, ẹ ò kúrò ní kíláàsì kan náà - Àwọn ọ̀dọ́
- Ọmọ ìkókó yìí bẹ̀rẹ̀ ǹkan oṣù l'ọ́mọ oṣù mẹ́rin, ó tún kojú àìsàn jẹjẹrẹ ilé ọmọ
Lẹyin eyi ni a kọ awọn orin ogo ilẹ wa ati ẹ̀jẹ́ fun orilẹ-ede ni eyi ti gbogbo ọmọ Naijiria maa n ka nibi eto akanṣe ati nile iwe.
Ṣaaju ni minista fun ifitonileti, Lai Mohammed fẹ̀sùn kan àwọn ènìyàn Naijiria pé ọ̀pọ̀ wọn ni kò orin ògò àti ẹ̀jẹ́ orílẹ̀-èdè wa!
Mo ṣe Ileri fun orilẹ-ede mi Naijiria ni ila akọkọ ninu ẹ̀jẹ́ naa to ṣe idanimọ ati imọsilara pe Naijiria yii, ti gbogbo wa ni.
Lati jẹ olododo ati olotitọ eniyan
Ẹni ti o ṣee fi ọkan tan naa tun jẹ awọn amuyẹ to le mu idagbasoke ba Naijiria ti gbogbo wa ba mu ileri yii ṣẹ.
Ẹ jẹ ki gbogbo wa lọ tun orin ogo Naijira ati ẹjẹ yii kọ lede abinibi wa, ki a si fi gbolohun inu rẹ kọ awọn ewe iwoyi ki ọjọ iwaju Naijiria le dun ju bayii lọ.