You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Nigeria's budget and borrowing: Bí a kò bá yá owó, Nàìjíríà ò bá má bọ́ nínú ìfàsẹ́yìn ọ̀rọ̀ ajé - Mínísítà ètò ìsúná
Minisita fun eto isuna, aba isuna ati aato lorilẹede Naijiria, Zainab Ahmed ti tun gboriyin fun bi ijọba ṣe n ya owo.
Minisita ọhun ni ẹyawo ọhun wulo gidi lati yọ Naijiria kuro ninu gbese.
O sọ eyi lọjọ Ẹti nigba ti wọn n ṣe agbeyẹwo itagbangba ati atupalẹ iwe aba eto isuna ọdun 2022.
- Òrùka ìgbéyàwó,ìlẹ̀kẹ̀ ìdí àti àwọn nkán míràn tàwọn eléwé ọmọ fí n ṣètò ìfètòsọ́mọbíbí
- Mo dúpẹ́ pé Ọlọrun kò jẹ́ kí àwọn ọmọge tí mo kọ́kọ́ dẹnu ìfẹ́ kọ gbà láti fẹ́ mi - Mike Bamiloye
- Ṣé o mọ̀ pé o leè kó Covid pẹ̀lú ọmọ ìka ẹ̀sẹ̀ rẹ̀ láì mọ̀?
- Ààrẹ Buhari, wá ọ̀nà míràn látí wá owó fún ètò ìṣúná 2022, ẹ̀yáwó ojojúmọ́ tí pọ̀jù- Ilé Ìgbimọ̀ Aṣòfin
- Wàhálà bẹ́ sílẹ̀ nílé aṣòfin, káńsẹ́lọ̀ obìnrin ní alága ìjọba ìbílẹ̀ ló pàṣẹ pé káwọn jàndùkú fa aṣọ òun ya.
- Ṣé lóòtọ́ ni ìjọba orílẹ̀-èdè Benin ti gba àbọ̀dè lórí ẹjọ́ sunday Igboho?
Minista ni: "Pẹlu iriri ifasẹyin lẹẹmeji, a ti ni lati na ọpọlọpọ owo kuro ninu ifasẹyin ọrọ aje eyi to da kun idagbasoke gbese wa,".
Minisita sọ eyi nilu Abuja lẹyin ọjọ ti aarẹ Buhari gbe aba eto isuna ọdun 2022 lọ siwaju ile igbimọ aṣofin.
O ni ko ṣeeṣe ki jijade ninu ifasẹyin yii yara bẹẹ naa bi kii ba ṣe pe ijọba n ri owo lo paapaa eyi ti awọn gbese owo yiya ṣe iranlọwọ fun.
Ṣaaju akoko yii, minisita naa ti sọ pe owo ti orilẹede Naijiria yoo fi gbọ bukata eto isuna ọdun 2022 eyi to to N6.258 triliọnu amọ nipasẹ ẹyawo tuntun ni yoo jẹ.
- Àbádòfin ìṣúná 2021 ré kọjá ìpele ìkejì nílé aṣòfin àgbà
- Ọjọ́ iwájú ní kí o wò, má fi gbèsè owóyàá bá ọjọ́ ọlá àwa ọmọ Nàìjíríà jẹ́-ẹgbẹ́ MAN
- Wo kókó mẹ́ta nípa àbá ìsúná ₦16.39trn fún ọdún 2022 tí Buhari gbé lọ sílé aṣòfin
- Kókó mẹ́rin tó jẹyọ lẹ́yìn ìpàdé àwọn adarí ẹgbẹ́ òṣèlú PDP
- Àjọ WHO gbé abẹ́rẹ́ àjẹsára àìsàn ibà jáde fún ilẹ̀ Afrika
- Wo kókó mẹ́ta nípa àbá ìsúná ₦16.39trn fún ọdún 2022 tí Buhari gbé lọ sílé aṣòfin
Igbesẹ yii mu ki awọn eeyan gbana jẹ kaakiri Naijiria. Awọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu alatako gan fesi pe igbesẹ naa atawọn ẹyawo mii ti ijọba apapọ n ṣe loriṣiriṣi nilo amojuto.
"Ẹgbẹ oṣelu wa rii gẹgẹ bi iwa aburu pe awọn eeyan to mọ pe awọn ko ni to ọdun meji mọ lati kuro lori aleefa wa n ko gbese jọ bi ẹni n mọ oke gelete.
O ni: dipo ti o yẹ ki wọn wa ọna ati mu adikun gbese ti wọn ti ko ba orilẹede.
Egbẹ oṣelu PDP sọ eyi lẹyin ti aarẹ Buhari beere fun ki ile aṣoin buwọlu ẹyawo $4 bilọnu ati #710 miliọnu lati di gbese isuna ti ọdun 2021.
Amọ Zainab ti ṣalaye pe ẹyawo gangan lo ti ran ijọba lọwọ lati pese awọn nkan amayedẹrun ki ọrọ aje le gberu sii.
"Yiyawo ṣe pataki lati mu wa ri awọn owo to yẹ na ati lati doko owo fun awọn eniyan", Zainab ṣe afikun yii.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, iṣoro aabo ni Naijiria to n peleke sii yii, ijọba nilo lati ya owo.
"Eyi to tun wa buru jai ni pe ogun ti Naijiria n ba ipenija abo yii ja kii ṣe kekere jakejado orilẹede eyi si ti ko ọpọlọpọ inawo ba rira nkan ijagun".
Minisita tun mẹnu ba bi awọn ọmọ Naijiria ṣe n paya lori owo ti ijọba n ya, o ni "o ṣi wa ni odinwo ohun ti wọn le ya torinaa ki ẹnikẹni ma ṣe bẹru".
- Agbébọn yìnbọn pa akẹ́gbẹ́ rẹ́ lásìkò ìjínígbé tí wọ́n kójú Àmọ̀tẹ́kùn
- Wàhálà bẹ́ sílẹ̀ nílé aṣòfin, káńsẹ́lọ̀ obìnrin ní alága káńsù ló pàṣẹ káwọn jàndùkú fa aṣọ òun ya.
- Kí ni òṣèré Chiwetalu Agu ṣe tí àwọn ológun gbé e jàǹtò? Ẹṣẹ tí wọn kà síi lọrùn rèé
- Àpẹ́rẹ́ àìsàn tó ń fa àrùn jẹjẹrẹ pọ̀ lára àwọn obinrin tó wà ní ìlú Ibadan - Ìwádìí fìhàn
- Àwọn Òṣèré fíìmù Yorùbá tẹ́ ò ro tó tí jápaa lọ ìlú Òyìnbó rèé