Ijero Ekiti Health Tech: Ìjọba Ekiti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí ìṣẹ̀lẹ̀ tó gbé akẹ́kọ̀ọ́ 100 dé ilé ìwòsàn

Gomina Fayemi
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Ijọba ipinlẹ Ekiti ti paṣẹ pe ki ọga agba ileewe giga College of Health Sciences, Ijero-Ekiti, kuro lẹnu iṣẹ naa, lẹyin ti awọn akẹkọọ kan di eero ile iwosan.

Ọjọbọ ni Gomina Kayọde Fayẹmi paṣẹ pe ki Ọmọwe Cecilia Adebayọ lọ ọ rọkun lile, titi igbimọ oluwadii yoo fi pari iwadii lori nkan to fa aisan to deedee kọlu akẹkọọ to le ni ọgọrun.

Skip X post
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post

Ṣaaju ni iroyin jade pe awọn ikọ afinko kan gba aṣẹ lọwọ awọn alaṣẹ ileewe naa lati fin oogun apakokoro sinu ọgba ileewe, lasiko ti awọn akẹkọọ n ṣe idanwo lọwọ.

Lẹyin ti wọn fin oogun naa, ti igbagbọ wa pe nitori Covid-19 ni wọn fi ṣe bẹ ẹ, ni awọn akẹkọọ naa bẹrẹ si ni dubulẹ aisan.

Eyi si lo mu ki awọn akẹkọọ ile ẹkọ giga naa ba ọpọ dukia jẹ láti fẹhonuhan lẹyin tawọn akẹẹgbẹ wọn kagbako.

Àkọlé fídíò, Democracy day 2021: Kí ni Nàìjíríà ti jèrè lára gbogbo ààrẹ tó ti jẹ látọdún 1999?
Àkọlé fídíò, King Sunny Ade's son: Ohùn orin bàbá mi nìkan kọ ni l’Ọlọrun fún mi, ijó bíi kòkòrò ni ṣáá

Awọn oṣiṣẹ panapana ijọba apapọ lo wa fin ile ẹkọ naa lasiko tawọn akekọọ n ṣe idanwo lọwọ.Kẹ́míkà oogun ipakokoro náà ni a gbọ pe o mu kí awọn akẹkọọ kan ṣubu nigba ti awọn miran ko le ṣọrọ daadaa.Koda, iroyin tun sọ pe ori lo ko awọn oṣiṣẹ panapana ọhun yọ pẹlu atilẹyin awọn ọlọpaa.

Diẹ lara awọn akẹkọọ naa re e ni idubulẹ aisan

Oríṣun àwòrán, Ekiti state ministry of health and human sciences

Àkọlé àwòrán, Diẹ lara awọn akẹkọọ naa re e ni idubulẹ aisan

Ẹwẹ, kọmiṣọnna eto ilera ipinlẹ Ekiti, Oyebanji Filani ti ṣabẹwo s'awọn akẹkọọ naa nile iwosan.O ni awon kan tiẹ ti gbadun ti wọn si ti lọ si ile wọn.Kọmiṣọnna ni ijọba yoo moju to awọn to si n gba itọju nile iwosan titi ti ara wọn yoo fi ya.

Oyebamiji Filani ati awọn mii

Oríṣun àwòrán, Ekiti state ministry of health and human sciences

Àkọlé àwòrán, Kọmisaana fun eto ilera ni Ekiti, Oyebamiji Filani ti bẹ awọ̀n akẹkọọ naa wo ni ile iwosan
Àkọlé fídíò, 'Èmi ọmọ Ikorodu ọ̀ga, ọmọ aṣalẹ̀ jẹ́jẹ! Wo bí àwọn ọmọdé tó "tuush" yìí ṣe ń fi oríkì Yorùbá dábíra

O fikun ọrọ rẹ pe awọn to lọ fin ọgba ile ẹkọ gíga naa lasiko tawọn akekọọ n ṣe idanwo lọwọ ko ni ṣai foju ba ile ẹjọ.

Akọwe ikede fun gomina, Yinka Oyebọde sọ ninu ikede to fi sita pe ọsẹ meji ni igbimọ oluwadii naa yoo fi ṣe isẹ rẹ, bẹrẹ lati ọsẹ to n bọ.

Bakan naa lo sọ pe wọn ti sọ fun awọn oṣiṣẹ ileeṣẹ panapana ti ijọba apapọ to wa fin oogun naa, lati pada si ọfiisi wọn nilu Abuja.