You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Baba Ijesha: Yinka Quadri ní àwọn àgbààgbà òṣèré kò dákẹ́ lórí wàhálà láàrin Iyabọ Ojo ati Yomi Fabiyi
Agba ojẹ ninu awọn oṣere ni Naijiria, Yinka Quadri ti sọrọ lori itahusiraẹni to n waye laarin awọn oṣere meji, Iyabo Ojo ati Yomi Fabiyi lori ẹsun aṣemaṣe ti wọn fi kan oṣerekunrin, Olanrewaju Omiyinka, ti ọpọ eniyan mọ si Baba Ijẹsha.
Yinka Quadri ni lati igba ti iṣẹlẹ Baba Ijẹsha ti ṣẹlẹ ni awọn ko dakẹ gẹgẹ bi agba ninu ẹgbẹ awọn oṣere ni Naijiria , TAMPAN.
Ninu ọrọ rẹ, Quadri ni dajudaju ilẹ Yoruba ko fi aye gba ki nkan ma a daru nigba ti awọn agbaagba wa nibẹ.
- Saudi Arabia, Iran àti Egypt wà lára orile-ede àgbáyé tó ga jùlọ láti fi ikú ṣe ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ lọ́dún 2020
- Aàrẹ Joe Biden sọ̀rọ̀ fún ìgbà àkọ́kọ́ lórí ìja Isreal àti Palestine
- Àwọn Olùkọ́ Akure pegedé lórí ètò Akomolede àti Aṣa lórí BBC Yorùbá
- Ẹ̀yìn tí ẹ̀ ń pè fún Yoruba Nation, òpè ní yín, ẹ kò ní ìmọ̀- Ladoja
- Ṣé lóòtọ́ ni Iyabo Ojo ti bẹ Yomi Fabiyi lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha tó wà ní Panti?
- Ohun tí mo fẹ́ ṣe fún ẹbí ẹ̀gbọ́n mí, Dare Adeboye rè é ... -Leke Adeboye
- Obìnrin ẹni ọdún 67 di àwátì lásìkò tó ń lọ sí ìṣọ́ òru
Yinka Quadri ni: ''Ni ọlọkan o ju ọkan ni awọn agbaagba oṣere n ba Yomi Fabiyi ati Iyabo Ojo sọrọ lati pe fun alaafia lori ọrọ yii''
''A n pe wọn ni ẹyọ kọọkan bi a ṣe sunmọ wọn si, a ko dakẹ rara''
Amọ Yinka Quadri ni ọrọ awọn mejeeji ti wa ni ọdọ awọn alakoso ẹgbẹ awọn oṣere, ti wọn si n gbe igbeṣẹ lori rẹ.
Agba oṣere naa fikun wi pe laipẹ yii ni ẹgbẹ yoo sọrọ lori rẹ, ti wọn yoo si fi atẹjade lede.
Baba Ijesha yóò ṣì wà látìmọ́lé títí ilé ẹjọ́ yóò fi parí ìyanṣẹ́lódì- Kọmisọ́nnà Ọlọ́pàá
Kọmisọna Ọlọpaa ipinlẹ Eko, Hakeem Odumosu ti ni titi igba ti awọn oṣiṣẹ ile ẹjọ yoo pari iyanṣẹlodi wọn ni Baba Ijesha yoo fi wa latimọle.
Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Eko ti sọ pe awọn ko mọ ọ mọ ṣi fi oṣerekunrin, Olanrewaju Omiyinka Baba Ijẹsha, si ahamọ lai gba beeli rẹ.
Kọmisọnna ọlọpaa, Hakeem Odumosu, sọ ọrọ yii gẹgẹ bi esi si iwọde ti akẹẹgbẹ Baba Ijẹsha, Yomi Fabiyi ṣe ni ẹka ileeṣẹ ọlọpaa to n wadii ẹsun ọdaran, Panti, Yaba.
Ọjọru ni Fabiyi ati awọn eeyan kan ṣe iwọde naa lati beere fun gbigba beeli Omiyinka.
- Ṣé ǹkan oṣù rẹ ń dà hìì hìì lẹ́yìn tóó gba abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19? Ẹ gbọ́ tuntun lẹ́nu àwọn Dókítà
- Kí ló mú Yomi Fabiyi àti Iyabo Ojo máa sá aṣọ ìdọ̀tí ara wọn síta?
- Wo bí ìwọ́de Yomi Fabiyi nítorí ọ̀rọ̀ Baba Ijẹsha to wa ni àhámọ̀ ọlapàá ṣe n lọ nílùú Eko
- Davido sí Yomi Fabiyi: Mùmú ni ẹ́
- Iyabo Ojo pé Yomi Fabiyi lẹ́jọ́, ìdí abájọ rèé
- Ọkùnrin kan bí ẹgbẹẹgbẹ̀rún ni mi, àmọ́ o le darapọ̀ mọ́ ìwọ́de fún Baba Ijẹsha tí o ba tako ìfìyàjẹni
- Ikú kò m'ọmọdé, kò màgbà, ẹ gbàdúrà fún ìdílé mi àti aya pẹ̀lú ọmọ olóògbé- Pásítọ̀ Adeboye
Ṣugbọn ṣa, kọmisanna ọlọpaa naa sọ pe imọran ileeṣẹ eto idajọ lo mu ki awọn o sẹ fi afurasi naa si ahamọ.
Eyi ti ko ṣẹyin bi awọn oṣiṣẹ ile ẹjọ ṣe wa ni iyanṣẹlodi.
Lasiko iwọde to ṣe, Yomi Fabiyi sọ pe ifiyajẹni ati fifi ẹtọ ẹni dun-un ni bi awọn ọlọpaa ko sẹ gba beeli akẹẹgbẹ oun.
Ninu alaye rẹ, kọmisanna ọlọpaa sọ pe ileeṣẹ ọlọpaa ti pari iwadii rẹ lori ẹsun ti wọn fi kan Baba Ijẹsha pe o ba ọmọ ọdun mẹrinla ni ibalopọ.
"Nigba ti wọn ṣe iwọde wọn de SCIID, igbakeji kọmisanna to n dari ẹka naa, DCP Adegoke Fayoade ba wọn sọrọ."
"O sọ fun wọn pe nigba ti a pari iwadii wa, a fi abajade rẹ ranṣẹ si ileeṣẹ eto idajọ fun imọran. Imọran ti wọn si gba wa ni pe ka ṣi fi afurasi naa si ahamọ, titi ile ẹjọ yoo fi bẹrẹ iṣẹ pada."
- Ẹ ò lè rí Covid-19 nínú ìjọ mi, ẹ má fi abẹ́rẹ́ rẹ̀ lọ̀ mí - Oyedepo
- Bó ṣe nípasẹ̀ ọkada ni tàbí ọkọ̀ ojú omi tàbí láti inú ihò ilẹ̀, ẹ wá ọ̀nà láti fi Naijiria sílẹ̀- Pasitọ Paul Adefarasin
- Ọkùnrin kan bí ẹgbẹẹgbẹ̀rún ni mi, àmọ́ o le darapọ̀ mọ́ ìwọ́de fún Baba Ijẹsha tí o ba tako ìfìyàjẹni
- Kàyèéfì! Wo ìdí tí àlùfáà ìjọ Aguda fi ń kó ère ìṣẹ̀nbáyé pamọ́?
- Ẹni tó bá ní láàkàyè, a mọ ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn, àwà ti kọ lẹ́tà, èsì t'Ọ́lọ́pàá sì fún wa rèé - Yomi Fabiyi
Ọgbẹni Odumosu ṣalaye pe o ṣe e ṣe ki ileeṣẹ eto idajọ tun ero rẹ pa lori bi Baba Ijẹsha ṣe wa ni atimọle, ti iyanṣẹlodi ẹgbẹ JUSUN, ba fi tẹsiwaju kọja bo sẹ yẹ.
O sọ pe awọn oṣiṣẹ ile ẹjọ ti gba lati ma a ṣiṣẹ fun ọjọ mẹta laarin ọsẹ, ti wọn o si ma a fi ọjọ meji to ku yan iṣẹ lodi.
"Ṣugbọn, ti ile ẹjọ ba ṣi fi wa ni titi pa, ileeṣẹ eto idajọ le gbe igbesẹ miran, amọ lọwọlọwọ, imọran ti wọn fun wa ni a n tẹle."
- Wo bí ìwọ́de Yomi Fabiyi nítorí ọ̀rọ̀ Baba Ijẹsha to wa ni àhámọ̀ ọlapàá ṣe n lọ nílùú Eko
- Ogójì èèyàn ti pàdánù ẹ̀mí wọn nítorí ìjà tó ń wáyé láàrín Israel àti Palestine ní Lod
- Ẹ̀yin ọmọ Naijiria, ẹ gbé ohùn àdúrà sókè nítorí ètò ààbò Naijiria - Buhari
- Iyabo Ojo pé Yomi Fabiyi lẹ́jọ́, ìdí abájọ rèé
- Ohun tí mo fẹ́ ṣe fún ẹbí ẹ̀gbọ́n mí, Dare Adeboye rè é ... -Leke Adeboye