“Ojú mi kòró báyìí ni àwọn ọ̀rẹ́ mi mẹ́ta kú sínú odò”

Ọjọ manigbagbe ni Ọjọ Kẹjidinlogun, Oṣu Karun un, ọdun 2022 ti ọfọ ṣe ni ilu Kano nibi ti awọn ọdọlangba mẹta ti ri sinu odo adagun ti wọn ti lọ wẹ.
Ọkan lara awọn ti iṣẹlẹ naa ṣoju wọn ni oun wa nibẹ nigbati awọn ọrẹ oun mẹtẹẹta si ku sinu omi.
Musa Abubakar, ẹni ọdun marundinlọgbọn, Isyaku Bashir, ẹni ọdun mẹtalelọgun ati Nazifi Ibrahim ni wọn sọ ẹmi wọn nu sinu adagun odo ni nkan bi aago mọkanla.
- Ki láwọn olóṣèlú Nàìjíríà rí tí wọ́n fi ń ṣé àbẹ̀wò sí ìyá arúgbó yìí ní Katsina?
- Alága ẹgbẹ́ ADP l’Ekiti ní òun kò ṣe ẹgbẹ́ mọ́ ṣáájú ìbò gómìnà l'óṣù Kẹfà
- Ikọ ajínigbé jí ìyàwó ọ̀sìngín gbé wọ́n f'ipá bá a lòpọ̀ làìmọye ìgbà, àṣírí tú!
- Ohun tó yẹ kí ìjọba ṣe nìyí bí wọ́n ṣe ń dá ẹ̀jọ́ ìkú Deborah Samuel- Agbẹjọrò Kayode Ajulo
- A bá òkú Akẹ́kọ̀ọ́ Poly Ibadan nílé ìyàgbẹ́ to ṣì dì ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀ mú - Aráàdúgbò
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Eko fòfin de ọ̀kadà ní ìjọba ìbílẹ̀ mẹ́fà
- Ilé ẹjọ́ wọ́gilé àfikún ẹjọ́ tí ìjọba àpapọ̀ pè tako Nnamdi Kanu
- Wo àwọn èèkàn ìjọba márùn ùn tí wọ́n fẹ̀sùn àjẹbánu kàn lábẹ́ ààrẹ Buhari
- Ẹ kò gbọdọ̀ mu igbó àti sìgá lẹ́nu iṣẹ́ mọ́ – Makinde kìlọ̀ fáwọn ọmọ ẹgbẹ́ onímọ́tò
Awọn mẹtẹẹta ni wọn jọ wa fun Majisi, eleyii to tunmọ si pe wọn fẹ yin Muhammed, pẹlu igbagbọ pe wọn yoo gba oriyin ni aye to n bọ tabi alujanna.
''Awọn ara agbegbe Karaye lo pe wa si ibi ayẹyẹ naa, to si yẹ ka pada si Bishi ni ọjọ naa, amọ wọn bẹ wa pe ka sun mọju nitori ilẹ ti su ni Karaye.''
''Ni aarọ ọjọ naa bi awọn eniyan ṣe n pẹ ni baluwẹ ni agbegbe Karaye, ni ọkan lara wọn wa gba wọn niyanju pe ki wọn lọ si odo lọ wẹ.''
''A ko kọkọ fẹ lọ amọ ọkan lara wa to pẹlu awọn to ku sinu odo naa ni ko si ohun ti yoo ṣẹlẹ.''
Bi iṣẹlẹ naa ṣe ṣẹlẹ ni yii…
Ọna meji ni odo naa ni ti a si yago kuro ni apa ibi to jin,a tun ri awọn ọmọde ninu omi naa ti wọn n ṣere.
Isyaku lo kọkọ bọ aṣọ to kosi odo ki Nazifi to darapọ mọ wọn, amọ o ripe wọn ko luwẹ wa si oke lo ba ko si inu odo lati lọ ranwọnlọwo.
Amọ oun naa ko pada soke ni a ba ripe nkan buruku ti bẹrẹ si ni ṣẹlẹ, bi a ṣe pariwo fun iranwọ niyẹn.
Amọ iranwọ ko wa ni kiakia, nigba ti awọn eniyan de lati doola ẹmi wọn, oku wọn ni wọn ba.
Idris to ṣalaye iṣẹlẹ naa ni oun ati ọrẹ oun ko lee wẹ ni awọn ko ṣe kosi odo lati doola ẹmi awọn ọrẹ oun.
Baba Musa lasiko to n sọrọ ni oun ko lee gbagbe bi ọmọ oun ṣe kuro ni ile, ki o to lọ si ilu Karaye.
O ni kii ṣe mọlẹbi nikan ni yoo ṣedaro Musa amọ gbogbo awọn ara adugbo ti wọn ma n wa gba owo ni ọwọ rẹ ni ṣọọbu POS rẹ.
Alukoro fun ileeṣẹ panapana ni Kano ni awọn ko gbọ nkankan ni kiakia amọ nigba ti wọn fi pe awọn, oku awọn ọmọ mẹta naa ni awọn yọ kuro ninu odo.
Bakan naa ni wọn kilọ fun awọn eniyan ki wọn ye ko wọ inu odo ti wọn ko bamọ nkankan nipa ẹ abi agbegbe naa.















