Ẹ kò gbọdọ̀ mu igbó àti sìgá lẹ́nu iṣẹ́ mọ́ – Makinde kìlọ̀ fáwọn ọmọ ẹgbẹ́ onímọ́tò

Seyi Makinde

Oríṣun àwòrán, Seyi Makinde

Ninu igbinyanju ijọba ipinlẹ Oyo lati ri pe alaafia jọba ní agbegbe ipinlẹ naa, Gomina Seyi Makinde ti kede awọn ilana ati ikilọ tuntun fun awọn ọmọ ẹgbẹ oni moto ni Ipinlẹ Oyo.

Makinde, to gba ẹnu komisona rẹ, Daud Sangodoyin sọrọ niluu Ibadan sọ pe ọpọlọpọ iwuwasi awọn ọmọ ẹgbẹ onimọto ati iwa orogun tí o da alaafia ilu laamu ni ko tẹ ìjọba ipinlẹ Oyo lọrun.

Ninu atesita kan tí akọroyin agba fun gomina Seyi Makinde buwọlu, o ni ajọṣepọ ìjọba ipinlẹ Oyo ati ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Oyo ni bii kí kede ilana tuntun fun awọn ọmọ ẹgbẹ oni moto.

Ilana tuntun naa ni ko fun awọn ọmọ ẹgbẹ oni mọto ni anfaani lati mu ida òfin lọwọ wọn, àti pe wọn gbọdọ tẹle eto ilana ofin orilẹ-ede Naijiria, ipinlẹ Oyo ati ti ajọ to n rí sì lilọbibọ ọkọ ni Ipinlẹ Oyo, OYRTMA.

Ilana tuntun naa ko faye gba àwọn ọmọ ẹgbẹ ònímọto lati mu siga, ọtí tabi lo ogun oloro lenu iṣẹ wọn.

Àkọlé fídíò, 'Ọ̀pọ̀ ìgbà l'èmí gan fẹ́ du àwọn ipò òṣèlú kan, bíì '2015, 2019' àmọ́ mo tẹ 'slow' torí bàbà mi, Akala náà ń jáde'

Sangodoyin tẹsiwaju pe awọn ọmọ ẹgbẹ onimọto gbọdọ maa wọ aṣọ to ni ountẹ ìjọba lara lẹnu iṣẹ, wọn si gbọdọ ṣe iṣẹ wọn lai si jagidijagan pẹlu ara ilu.

Komisona olopaa ni ipinlẹ Oyo, Ngozi Onadeko wa ṣe ni ikilọ fún àwọn ọmọ ẹgbẹ òní moto lati ri pe wọn jina sì iwa ibajẹ ati iwa jagidijagan nítorí awọn eleto abo ni ipinlẹ Oyo o ni faye gba ẹnikẹni to ru iru iwa naa.

Ninu ọrọ rẹ, alaaga fun awon ọmọ ẹgbẹ oni mọto l'Oyo, Alh Mukaila Lamidi ṣe ileri pe gbogbo ofin ìjọba ni ọmọ ẹgbẹ awọn ṣetan lati tẹle.

Àkọlé fídíò, Títí ayé yóò fi parẹ́, wọ́n ó máa sọ̀rọ̀ sí Ànọ́bì ni, wọ́n ó sì máa bú Jésù ni, ẹ wá gbọ́ òótọ́ ohun tí Quaran sọ – Akeugbagold