Sunday Igboho Herbalist: Agbófinró mẹ́fà ló wọ́lé wá gbé ọmọ mi láì mọ́ ibi tó wà
O ti to oṣu mẹta bayii ti awọn eeyan kan ti wọn funra si bii ọtẹlẹmuyẹ DSS wọ ile Dada Fasoto Arifanlajogun, ti o jẹ oniṣegun ati Babaláwo Sunday Igboho n'ipinlẹ Ekiti, ti ẹnikẹni ko si mọ ibi to wa.
Iya Dada, Olomitutu Fasoto, ti o jẹ yeye Ọṣun lo sisọ loju ọrọ yii fun akọroyin BBC Yoruba nilu Ikere Ekiti
Yeye Olomitutu ni ẹni ọdun mejidinlọgbọn ni ọmọ oun ti awọn agbofinro naa wa gbe lọ lai fi ẹsun kankan kan-an.
- Wọ́n gbé ọmọ mi tó jẹ́ Babaláwo Sunday Igboho, a kò mọ ìrìn rẹ̀ láti oṣù mẹ́ta
- A kìlọ̀ fún Sunday Igboho pé kó dákẹ́ àmọ́ kò gbọ́, èébú ló ń bú wa - Ooni Ife
- 'Ìròyìn òfegè ni! Olóyè Sunday Igboho kò ṣàbẹ̀wò sí Ọba Oluwo'
- Sunday Igboho, ìsáǹsá rẹ̀ kò lé sá mọ́ wa lọ́wọ́, mímú lá mú ọ - DSS fọwọ́ gbáyà
- Wo ìtàn ayé Sunday Igboho, gbajúmọ̀ ajìjàgbara fún ilẹ̀ Yorùbá
- Oríire ló jẹ́ fún Sunday Igboho bí ọwọ́ òfin kò ṣe bàá ní Nàìjíríà - Femi Falana
Olomitutu ni ọmọ oun lo jẹ oniwatutu, to si n ṣe iṣẹ iṣegun ibilẹ rẹ pẹlu ibẹru Ọlọrun amọ o jẹ ohun iyalẹnu pe wọn le wa gbe tori pe o n ba Sunday Igboho rin.
O ni oun ti bọ èṣù, ti oun si tun gbe gbogbo igbesẹ to yẹ ki oun gbe gẹgẹ bi ẹlẹsin abalaye amọ to ja si pabo.
- Níbo ní Sunday Igboho wà lẹ́yìn ìkọlù síle rẹ̀? Ọ̀pọ̀ ọmọ Nàíjíríà ń bèèrè
- Sunday Igboho tún dá Malami mọ́lẹ̀ fún ìgbà kejì nílé ẹjọ́
- Kìí ṣe tuntun pẹ ìjọba Buhari tí mú Sunday Igboho, àmọ́ ọ̀nà àbáyọ sí ìtúsílẹ̀ rẹ̀ rèé - Agbẹnusọ Sunday Igboho
- Kí ló dé tí DSS kó bàńtẹ́ òògùn, ba ilé Sunday Igboho jẹ́ lái fara pa?
- Ó lé yọrí sí ogun, tí ìjọba Naijiria bá fi ìyà jẹ Sunday Igboho bí ọ̀daràn - Gani Adams
O wa ke sawọn ọmọ Naijiria lati gba ọmọ oun silẹ ko le pada sọdọ aya ati ọmọ rẹ, ọmọ ọdun marun.
Nigba ti BBC Yoruba kan si agbẹnusọ fun ileesẹ Ọlọpaa nipinlẹ Ekiti, Abutu Sunday, o ni awọn ko gbọ nipa isẹlẹ naa, o si jẹ iyalẹnu pe lẹyin osu mẹta ni wọn sẹsẹ nileesẹ ọlọpaa sẹsẹ n gbọ.





