Elegushi Romance Fraud: Ọwọ́ tẹ abánikunlé tó fi orúkọ Ọba Elegushi lu obìnrin kan ní jìbìtì ₦51m

Oríṣun àwòrán, @PoliceNG
Afurasi meji to fi orukọ ọba Elegushi nipinlẹ Eko lu eeyan ni jibiti, ti wa ni ahamọ ọlọpaa
Ileesẹ ọlọpaa nipinlẹ Eko ti ṣa fihan ọkùnrin kan, Moses Olaitan ati ẹnikeji rẹ, Segun Omoshola fun ẹsun pe wọn fi orukọ ọba Elegushi lu jibiti.
Iroyin sọ pe nise ni àwọn eniyan naa n pe ara wọn ni Ọba Saheed Elegushi fun obinrin kan ti wọn pade lori ayelujara Facebook, titi wọn fi lu u ni jibiti miliọnu marundinlọgọta naira.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- A kò bá ti lé Baba Ijesha àmọ́ kìí ṣe ọmọ ẹgbẹ TAMPAN, a kò sì fọwọ́ sí ìwà tó wù - Mr Latin
- Ìjọ Islam fìwé pe Wòlíì Genesis bíi àlejò pàtàkì sí ìṣọ́ òru Lailatul Quadir, ariwo sọ
- Ẹ má da ẹnikẹ́ni lẹ́bi, ẹ jẹ́ ká wà ní ìṣọ̀kan láti borí ọ̀tá - Tinubu
- Ìwádìí fihàn pé Baba Ijesha bá ọmọdé lòpọ̀, a kò gba béèlì rẹ̀ - Ọ̀gá Ọlọ́pàá Eko
- Wo ohun mánigbàgbé mẹ́fà nípa Gbenga Adeboye lẹ́yìn ọdún 18 tó kú
- Ọjọ́ àkọ́kọ́ tí Baba Ijesha bá ọmọ mi lòpọ̀ ní mo ti mọ̀ àmọ́ kò sí ẹ̀rí - Princess
- Ọlọ́pàá kò lè dá wa dúró, á ṣe ìwọ́de Yoruba Nation l‘Abeokuta lọ́la - Yoruba Nation Agitators
- Ọ̀fọ̀ ńlá ṣẹ̀, ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ èèyàn tẹ ara wọ́n pa, ariwo ẹkún sọ
- Saidi Balogun figbe ta pé wọn ń ba òun lórúkọ jẹ́ lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha
- Iyabo Ojo gbé fídíò jáde nípa bí ọwọ́ ṣe tẹ Baba Ijesha
Ọga Agba ọlọpaa nipinlẹ Eko, Hakeem Odumosu sọ lasiko to fi ojú awọn afurasi naa han ni olu ileesẹ ọlọpaa to wa ni Ikeja pe, lẹyin ti wọn fi ẹjọ wọn sùn nileesẹ ọlọpaa, lẹyin oṣu mẹta tí wọn da ọ̀ràn naa, ni ọwọ awọn ọtẹlẹmuyẹ tẹ Segun ati Olaitan.
Ọkan lara awọn afurasi naa, Olaitan sọ pe oun fi orukọ ọba naa ṣi oju opo ibanidọrẹ lori Facebook, ti oun si bẹrẹ si ni fi àwọn aworan rẹ sibẹ lati fa oju awọn to n wa ọkọ mọ́ra.
Nipasẹ bẹẹ si ni obinrin ti wọn lu ni jibiti fi bọ si panpẹ wọn.
Olaitan ṣalaye pe, obìnrin naa ba oun sọrọ lori Facebook pe oun fẹ ẹ fẹ ọba ni ọkọ.
"Mo sọ fun pe to ba fẹ ẹ fẹ ọba, o gbọdọ ṣe àwọn nkan ibilẹ diẹ, o si gba lati ṣe bẹ ẹ.
" O sọ fun mi pe ki n fi nọmba apo asunwọn banki mi ránṣẹ si oun, sugbọn mi o ni. Eyi si lo mu mi fi ọrọ lọ Segun, to wa nọmba akanti ta fi gba owo naa."
Olaitan sọ pe miliọnu meji aabọ Naira ni wọn san fun oun, ati pe nígbà ti ọwọ tẹ ẹ, ni oun to mọ pe miliọnu mọkanlelaadọta ni obinrin naa san.
O sọ pe nọ́mbà foonu oun ni awọn ọlọpaa tọpinpin rẹ, ti ọwọ fi tẹ oun lasiko ti oun n palẹmọ fun ayẹyẹ ọjọ ibi oun.
Ni ti Segun to wa akanti ti wọn fi gba owo naa, o sọ pe lootọ ni oun mu lọ si ọdọ awọn to pese akanti naa.
Sugbọn o ni miliọnu mẹta aabọ Naira ni wọn fun oun, iyalẹnu si lo jẹ fun oun nigba ti awọn ọlọpaa sọ pe miliọnu mọkanlelaadọta Naira ni obìnrin naa fi ránṣẹ.
Bẹẹ ba gbagbe laipẹ yii ni Oluwo tilu Iwo, Ọba Abdulrasheed Adewale Akanbi naa figbe bọnu pe, awọn eeyan kan n gba awọn obinrin to nifẹ lati di ayaba ni aafin oun lori Facebook pẹlu orukọ oun.














