Slain Ekiti Police woman: Ìyá rẹ̀ ní àìrìṣẹ́ṣe ló mú kí Bukola Olawoye gba iṣẹ́ ọlọ́pàá
Adura ti ẹda kọọkan maa n gba ni pe ohun ta jẹ la n wa, ka ma pade ohun ti yoo jẹ wa.
Amọ adura yii ko gba rara fun obinrin ọlọpaa kan nipinlẹ Ekiti to lọ sẹnu isẹ lọjọ ti wọn n se atundi ibo sile asoju sofin ilẹ wa.
Obinrin ọlọpaa naa, Sajẹnti Bukola Olawoye lo bawọn sisẹ agbofinro lọjọ Satide, Ogunjọ osu Kẹta ọdun 2021 nibi atundi ibo ẹkun Ila oorun Ekiti sile asoju sofin.
- Ìtàn tó rọ̀ mọ́ òwe ‘aṣọ kò bá Ọ́mọ́yẹ mọ́...’ rèé
- Afọnja, ẹni tó finú wénú ní Ilọrin, àmọ́ tó jẹ iwọ
- Ọọ̀ni obìnrin, Lúwòó Gbàgídà rèé, akọni tó ń gun ọkùnrin ní ẹṣin rìn
- Ìtàn Ọba Yorùbá tí wọ́n yẹgi fún torí ó jí ọmọ gbé ṣe ètùtù
- Mọ̀ síi nípa Shina Rambo tó pàdé Jesu lọ́gbà ẹ̀wọn lẹ́yìn tó ti jalè
- Ogun Àgbẹ́kọ̀yà, ìjà òmìnira fáwọn àgbẹ̀ ni àbí ìfẹ̀míṣòfò?
- Irú èpè wo ni Aláàfin Aolẹ ṣẹ́ fún ìran Yorùbá?
- Àwọn ọba Yorùbá kan rèé tí wọ́n rọ̀ lóyè, tí ọba míràn jẹ lójú ayé wọn
Bukola ni ọta ibọn ba lasiko ti rogbodiyan gbode nibi atundi ibo naa, to si jade laye lọjọ Keji nile iwosan to ti n gba itọju, eyi to mu ki wọn so eto idibo naa rọ.
BBC Yoruba fẹsẹ kan de ile oloogbe Olawoye, lati mọ bi adanu obinrin ọlọpaa naa se ri lara wọn.
Nigba ti wọn n ba wa sọrọ, iya ati alagbatọ obinrin naa ni airisẹse lo mu ki Bukola lọ gba isẹ ọlọpaa, ti oun si ri iran iku rẹ ni kete ti wọn yinbọn mọ.
- "Àwa ní ọlọ́sìn ẹja tó ga jùlọ ní Nàíjíríà àmọ́ ìjọ́ba Kwara ń gbógun tì wá"
- Kí inú màmá mi le dùn ni mo ṣe kọ́ iṣẹ́ ọkọ̀ kíkùn - Modupe Olagunju
- Wo ìyàtọ̀ tó wà láàrin Ìjálá, Ìrèmọ̀jé àti oríkì ọ̀pọ̀ ẹranko ijù
- "Mo n bẹ ọlọ ata, òpó iná, tọ̀ sínú ẹ̀yìn iná lálẹ́, kí ń má baà tọ̀ sílé lóru"
- Torí àti ṣe Kòkò irin, bí mo ṣe máa ǹ fara yá iná ní gbogbo ìgbà nìyìí - Amokoko Saki
Wọn wa n bẹ ijọba lati se awari ẹni to yinbọn mọ obinrin naa, tii se ẹni ọdun mẹtalelọgbọn, to si fi ọmọ meji silẹ saye lọ.
Kọmisana ọlọpaa nipinlẹ Ekiti naa ni oun ri isẹlẹ naa bii eyi to wu Ọlọrun nitori gbogbo eto to yẹ ni awọn se lati dena rogbodiyan lasiko ibo naa.





