Orisabunmi, Ibidapọ-Obe, Akin Olugbade, Martins Kuye, Lateef Jakande: Àwọn eèkàn ọmọ Yorùbá tó ti jáde láyé lọ́dún 2021 nìkan

Oríṣun àwòrán, others
Wo àwọn eèkàn ọmọ Yorùbá tó ti jáde láyé lọ́dún 2021 nìkan
Ọdun to ti mu ọpọlọpọ la oriṣiriṣi nnkan kọja ni ọdun 2021 jẹ bi o tilẹ jẹ pe ko tii ju ọsu mẹta lọ ti ọdun naa bẹrẹ.
Ọpọlọpọ to ku ni iku wọn ko ṣẹyin ajakalẹ arun COVID-19 ti awọn miran si tun ku iku miran yala nitori ọjọ ogbo, ikọlu awọn agbebọn darandaran, ijamba ọkọ tabi awọn aisan miran.
Eyi ni akọsilẹ awọn orukọ awọn eekan ọmọ Yoruba to ti di araalẹ laarin oṣu mẹta akọkọ lọdun 2021.
- Wọn yóò yẹgi fún àwọn ọmọ Nàìjíríà méjì lórí ikú ọmọbìnrin Takoradi tó dàwátì ní Ghana
- Ọpẹ́lọpẹ́ àjẹsára, ó yẹ kí n ti kú lẹ́yìn tí àwọn jàǹdúkú ṣá mi ní àdá - Oyinkansola Elebuibon
- Ilé ẹjọ́ tú ìgbéyàwó ọlọ́mọ mẹ́jọ ká nítorí pé ọkọ rí àwọn òbí ìyàwó fín
- Gbèǹdéke ẹ̀mí gígùn àwọn ọmọ Naijiria kò ju ọdún 54 lọ - Ẹgbẹ́ àwọn Dókítà
- Ta ni Ousmane Sonko, tí wàhálà bẹ́ sílẹ̀ ní Senegal lẹ́yìn tí ìjọba fòfin mú u?

Oríṣun àwòrán, @Ibidapo-Obe
1.Ọjọgbọn Ibidapọ-Obe:
Purofẹsọ Ibidapọ-Obe ni giwa faisiti ilu Eko, UNILAG tẹlẹ.
Bakan naa lo tun fi igbakan ri jẹ giwa fun fasiti Alex Ekwueme Federal University ni ilu Ndufu-Alike.
Ọjọgbọn Oyewusi Ibidapo-Obe jade laye ni ọjọ kẹta, oṣu kini, ọdun 2021.
Ohun ti araye gbọ ni pe aarun COVID-19 lo ṣokunfa iku rẹ.
Iyalẹnu nla ni iku rẹ jẹ fun ọpọlọpọ awọn eeyan paapaajulọ lagbo ẹkọ lorilẹede Naijiria ati lagbaye.

Oríṣun àwòrán, @Orisabunmi
2. Arabinrin Folake Aremu (Orisabunmi):
Eekan elere itage ati sinima ni arabinrin Folake Aremu ti ọpọlọpọ mọ si Orisabunmi.
Ọjọ karun un, oṣu kini ọdun 2021 ni Oriṣabunmi jade laye.
Iku rẹ si fẹ afẹfẹ ibanujẹ nlanla si agbo awọn oṣere tiata.
Ọmọ ilu Olla ni ipinlẹ Kwara ni Oriṣabunmi, ẹni õgọta ọdun si ni nigba to jade laye.
Lẹyin oṣu mẹrin ti ọkọ rẹ tẹlẹ, Jimoh Aliu jade laye ni iku mu oun pẹlu lọ.

Oríṣun àwòrán, @Folabi Olumide
3. Ọjọgbọn Folabi Olumide:
Ọjọgbọn Folabi Olumide ni giwa akọkọ fun fasiti ipinlẹ Eko, LASU, ọjọ Ẹti ọjọ kẹjọ oṣu kini ni wọn ju awà silẹ.
Aisan ranpẹ lo muu lọ si alakeji lẹni ọdun mọkanlelọgọrin.
4. Aare Boluwatife Akin-Olugbade:
Aare Boluwatife Akin-Olugbade ni Aare Ona Kakanfo ti Owu nilu Abẹokuta.
Lagbaye ni wọn ti mọ si ọkan gboogi lara awọn to nifẹ ọkọ Rolls-Royce julọ.

Oríṣun àwòrán, @Akin-Olugbade
Ọjọ kẹrinla, oṣu kini, ọdun 2021 ni ajakalẹ arun COVID-19 wọle mu u lọ.
Amofin to kọṣẹmọsẹ gboye ọmọwe ninu imọ ofin nipa ileeṣẹ ni ni fasiti Cambridge.
Ọkọ Rolls Royce mẹwaa ni oun nikan niti owo rẹ n lọ si ẹgbẹlẹgbẹ biliọnu naira.
Ẹni ọdun mẹrinlelọgọta ni ki ọlọjọ to de.
- A ti rí Ọọ̀nì ''crocodile'' 27 nínú àwọn tó sálọ, àmọ́ a ṣì ń wá àwọn tó kù, ẹ̀yin ará ìlú, Ẹ ṣọ́ra!
- Lọ́ọ̀tọ́ ní Sunday Igboho wá sí igbó Ire-Ekiti láti bọ Ogun lákáyé!- Akọ̀wé ìpínlẹ̀ Ekiti
- Oral Sex: Bóo bá ń gba ẹnu ní ìbálòpọ̀, wo àìsàn tóo lè kó lójú ara rẹ
- Àwọn panápaná ti pa iná tó ṣẹ́yọ nídàjí òní nílé epo NNPC ní Akute nitòsí Berger báyìí
5. Martins Kuye:
Martins Kuyẹ fi igbakanri jẹ minisita fun ọrọ iṣuna lorilẹede Naijiria.
Eekan ẹgbẹ oṣelu PDP si ni pẹlu ki o to jadelaye ni ọjọ kẹtadinlogun oṣu kini ọdun 2021.
Onimọ nipa ibagnepọ ẹda( socioloist) ati ọrọ aje (economist) ni.
Igba meji ọtọtọ lo si gbiyanju ati di gomina ipinlẹ Ogun ṣugbọn ti ko bọ si ki ọlọjọ to de.

Oríṣun àwòrán, @Martins Kuye
6. Alhaji Lateef Jakande:
Gomina tẹlẹ fun ipinlẹ Eko, Lateef Jakande jade laye ni ọjọ kọkanla oṣu keji ọdun 2021.
Ẹni ọdun mọkanlelaadọrun ni Baba kekere nigba to jade laye.
Akọroyin to dantọ ni ki o to di gomina ipinlẹ Eko laarin ọdun 1979 si 1983.
Nigba to ya, o di minisita fun iṣẹ ode labẹ iṣejọba Ọgagun Sani Abacha laarin ọdun 1993 si 1998.
- Ilé ẹjọ́ tú ìgbéyàwó ọlọ́mọ mẹ́jọ ká nítorí pé ọkọ rí àwọn òbí ìyàwó fín
- Gbèdéke ẹ̀mí gígùn àwọn ọmọ Naijiria kò ju ọdún 54 lọ - Ẹgbẹ́ àwọn Dókítà
- Lọ́ọ̀tọ́ ní Sunday Igboho wá sí igbó Ire-Ekiti láti bọ Ogun lákáyé!- Akọ̀wé ìpínlẹ̀ Ekiti
- Ó ṣòro púpọ̀ láti mọ ayédèrú òṣìṣẹ́ LASTMA ní ìpínlẹ̀ Eko, ṣùgbọ́n..-Agbenusọ àjọ LASTMA
- Wòlíì Kasali gba Bunmi ìyàwó rẹ̀ àkọ́fẹ́ padà, ìjà parí!















