Ibrahim El-Zakzaky: Zeenat lùgbàdì covid-19 lọ́gbà ẹ̀wọ̀n, IHRC rọ Buhari kó tú òun àti ọkọ rẹ̀ sílẹ̀

Zeenat El-Zakzaky ti lugbadi arun coronavirus lọgba ẹwọn to wa pẹlu ọkọ rẹ, Ibrahim El-Zakzaky niluu Kaduna.
Ọmọkunrin kan ṣoṣo to ku fun olori awọm musulumi Shiite, Ibraheem Zakzaky ṣalaye pe iya oun ti n fi awọn apẹẹrẹ coronavirus han ki wọn to ṣe ayẹwo fun un.
Ọmọkunrin El-Zakzaky ni ayẹwo ti awọn dokita obi oun ṣe lo fihan pe mama oun ti lugbadi arun coronavirus.
- Igboho vs Fulani: Báyìí ni nǹkan ṣé ń lọ nílé Sunday Igboho lónìí
- Ẹ̀kún l'oúnjẹ́ mi ní ọ̀pọ̀ ìgbà lẹ́yìn tí ojú mi fọ́ ní JSS 3- Lawal Ayankemi
- Ẹ̀yin èèyàn ìpínlẹ̀ Oyo, mìmì kan kò lè mì yín lónìí- Makinde
- Ẹ wo ohun tí Seriki Fulani sọ fún gómìnà Makinde nípa Sunday Igboho
- Gbogbo ẹ̀yin Fulani darandaran tó wà ní ìgbó ìjọba ní Ondo, ọjọ méje lẹní láti pòórá - Gomina Akeredolu
- Àwọn Ọba ló rànṣẹ́ pè mi pé ìyá ìjínigbé àti ìpànìyàn yì tó gẹ́- Sunday Igboho
O ni awọn dokita ọhun tun ṣe oriṣiiriṣii irufẹ ayẹwo miiran fun iya oun lọgba ẹwọn.
Ibraheem ni o ṣe pataki lati fidi rẹ mulẹ pe ijọba ti dena mọ iya oun lati lọ gba itọju lori arun inu egungun orunkun(arthritis) ti o mu un fun ọpọ ọdun.
Ẹwẹ, ajọ ajafẹtọ ọmọniyan, IHRC ti kepe Aarẹ Muhammadu Buhari wi pe ko da El-Zakzaky ati aya rẹ silẹ lọgba ẹwọn lati le daabo bo wọn lọwọ arun coronavirus.
Bakan naa ni ajọ ọhun tun kọwe si ajọ iṣọkan agbaye, UNO lati sọ fun ijọba orilẹede Naijria pe ko fi wọn silẹ.
Ajọ IHRC ṣalaye siwaju si pe arun covid-19 ti iyawo El-Zakzaky ti ni bayii le wu awọn mii silẹ lara rẹ nitori ailera to ni.
Ajọ ajafẹtọ ọmọniyan naa ni ọgba ẹwọn ti olori awọn musulumi Shiite wa le ṣakoba nla fun ilera rẹ papaa julọ bi arun covid-19 ṣe n pọ si lojoojumọ yii.
IHRC sọ pe iwa to buru jai ni ijọba Naijiria hu lori bi o ti ju tọkọ-taya si ọgbọn wọn nigba ti ileẹjọ ko tii sọ pe wọn jẹbi ẹsun ti wọn fi kan wọn.
El-Zakzaky ati aye rẹ Zeenat ti wa ni ẹwọn fun ọdun mẹfa bayii.
- ''Ìjọba ìpínlẹ̀ Ondo kò bẹ̀rù idúnkokò mọ́ni iléeṣẹ́ ààrẹ lórí ọ̀rọ̀ àwọn Fulani darandaran''
- Ẹ̀yin èèyàn ìpínlẹ̀ Oyo, mìmì kan kò lè mì yín lónìí- Makinde
- Taa ni ọkùnrin 'tó tan mọ́ Naijiria' tó fún ọmọ Trump, Tiffany ní òrùka ìlérí ìgbéyàwó?
- Ààrẹ Joe Biden tí gba àwọn ọmọ Naijiria láàyé látí wá sàtìpó ní Amẹrika
- Alààfíà ló kú tí àwa Fulani ń wá ní Oyo báyìí- Miyetti Allah




















