Lai Mohammed: A ti gba 800 bílíọ̀nù padà lọ́wọ́ àwọn tó jíi kó, àwọn 1,400 ti dèrò ẹ̀wọ̀n

Oríṣun àwòrán, @thebridgenewsng
Ijọba apapọ ti sọ pe oun ti gba owo to le ni ẹgbẹrin bilọnu naira pada lọwọ awọn to jii ko.
Minisita fun eto iroyin at aṣa, Lai Mohammed lo kede bẹẹ nibi ipade awọn akọroyin kan to waye ni ilu Abuja.
O fi kun un pe egbeje eeyan lo ti n faṣọ penpe roko ọba bayii lẹyin ti aje iwa ajẹbanmu ṣi mọ wọn lori.
O ṣalaye pe "Gẹgẹ bi mo ṣe sọ tẹlẹ, ijọba to wa lode yii n doju ija kọ iwa jẹgudujẹra, a si ni ẹri lati gbe e lẹsẹ."
Minisita ọhun tẹ siwaju pe "Ijọba yii ni akọsilẹ awọn egbeje eeyan to wa ni ahamọ, bẹẹ ni a si ti gba owo to le ni ẹgbẹrin bilọnu naira pada, yatọ si awọn ohun ini ti agbẹsẹle."

Oríṣun àwòrán, @ScooperNG
- Irọ́ ni o, kò sí ẹ̀rí pé Hydroxychloroquine leè kojú àrùn Coronavirus- Ẹgbẹ́ àwọn adarí ilé ìwòsàn ní Naijiria
- Òtítọ́ lékè! Akinwumi Adesina bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀ṣùn jẹgúdújẹrá tí wọ́n fi kan - AFDB
- Ìjọba Nàìjíríà kéde ìsinmi ọlọ́jọ́ méjì f'ọdún Iléyá
- Ìyá Barakat fi ẹ̀mí ìmoore hàn sí gbogbo àwọn tó nawọ́ síi lẹ́yìn ikú ọmọ rẹ̀
O ni yatọ si gbigba owo ijọba ti awọn eeyan kan lu ni ponpo pada, ijọba to wa lode yii tun n ṣeto iyipada ọkan fun awọn ọmọ Naijiria ki iwa ajẹbanu lee di ohun igbagbe.
Lai pari ọrọ rẹ pe ki awọn to n bu ẹnu atẹ lu akitiyan ijọba to wa lode yii ronupiwada, ki wọn si dojukọ aṣeyọri ti ijọba n ṣe lati pana iwa jẹgudujẹra lorilẹ-ede yii.









