Babcock Sex Video: Láti ìgbà tí fásitì ti lé àkẹ́kọ̀ọ́ náà ló ti dùbúlẹ̀ àìsàn amọ́ ara rẹ́ ti dá

Oríṣun àwòrán, Babcock/Twitter
Arabinrin akẹkọọ fasiti Babcock ti fidio ibalopọ rẹ pẹlu ọrẹkunrin rẹ lu sori ayelujara ni ọdun sẹyin yoo lọ kawe si ileẹkọ fasiti loke okun.
Eyi ko ṣẹyin bi ileewe giga fasiti kan ni oke okun, ṣe fun arabinrin naa ni anfaani lati kawe lai san owo ileewe.
Dokita Ola Bukola to tun jẹ oluranlọwọ rẹ ni Niajiria, lo kede bẹẹ loju opo Twitter rẹ pẹlu afikun bukata ẹkọ rẹ naa ni oke okun ti gbe.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìtàn ọba Yorùbá tí wọn yẹgi fún torí ó jí ọmọ gbé ṣe ètùtù
- Ọdẹ ìbílẹ̀ ní Okeho pa adigunjalè mẹ́rin tó fọ́ báńkì, aráàlú dáná ṣun wọ́n
- Aláwàdà ni ọmọ mi láti kékeré, kò ṣẹ̀ṣẹ̀ máa gbé mi mọ́ra- ìyá ‘Mummy calm down’ (Toluige Olokoobi Babalola)
- Wo ìyàtọ̀ tó wà láàrin Bíbélì Yorùbá tí Kumuyi kọ sí èyí tó wà ńlẹ̀
- Ìkúnlẹ̀ abiyamọ, ìkókó mẹ́jọ kú nílé ìwòsàn lálẹ́ ọjọ́ kàn
- Dayo Amusa gbarata lórí bí agbófinró ṣe ń pa ọ̀dọ́ láì nídìí
Arabinrin naa ni Fasiti Babcock fi ọwọ oṣi juwe ile fun, nitori fọnran kan to lu ayelujara pa, nibi ti ọkunrin kan ti n ba lopọ.
Dokita Bukola ni lati igba ti iṣẹlẹ naa ti ṣẹlẹ ni arabinrin naa ti n gba iwosan.
Nibayii, Dokita naa ni saka ni ara rẹ da, ti o si tun ṣe daadaa ninu gbogbo idanwo ti o ṣe.
Dokita Brown ni afojusun oun fun arabinrin naa ni ki o yege, ki o si di ẹni nla ni awujọ lọjọ iwaju.

Oríṣun àwòrán, Babcock
O ti kọkọ fi lede ni Osu Kẹfa wi pe gbogbo eto ti n to lati ri wi pe arabinrin naa lọ si ileewe giga lai si idẹyẹsi fun wọn.
Nigba naa, o ni aye arabinrin naa ti yipada si rere lati igba ti wọn ti le kuro ni ileewe, to si yege ni ẹkọ rẹ ati ihuwasi rẹ.
Ọpọ ọmọ Naijiria lo tako igbesẹ fasiti Babcock nigba naa, lori bi wọn ṣe fi ọwọ osi juwe ile fun akẹkọbinrin naa ti wọn n ba lopọ ninu fidio to lu ori ayelujara pa.
- Ìpínlẹ̀ Oyo kéde àdínkù owó orí nítorí Covid 19
- Ìjọba àpapọ̀ kéde ọjọ́ tí ìdánwò NECO, NABTEB àti BECE yóò bẹ̀rẹ̀
- Keisha sàlàyé ìdí tó fi sunkún ní ìyàrá ìrántí nílé ẹlẹ́gbọ̀n ọ́n àgbà, ayé pariwo
- Ìjọba Èkó yóò fi òfin dè títà afẹ́fẹ́ gáàsì létílé láti dènà ìbúgbàmú láwùjọ
- Ìkúnlẹ̀ abiyamọ, ìkókó mẹ́jọ kú nílé ìwòsàn lálẹ́ ọjọ́ kàn
Fásítì Babcock lé akẹ́kọ̀ọ́bìnrin tó hàn nínú fídíò ìbálòpọ̀ lọ sílé
Saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe fasiti Babcock ti fọwọ oṣi juwe ile fun akẹkọọbinrin to wa ninu fọnran to lu ayelujara pa, nibi ti ọkunrin ati obinrin kan ti ni ibalopọ.

Oríṣun àwòrán, Faceboo/Babcock University
Agbẹnusọ fun ile iwe naa to ba BBC sọrọ ṣalaye pe, oṣu kẹrin ọdun yii awọn mejeeji ni ibalopọ ṣugbọn kii ṣe ninu ọgba ile iwe naa.
Ninu oṣu keji ọdun yii ni ile iwe naa kọkọ le ọkunrin to wa ninu fọnran lọ ile, lẹyin ti wọn fẹsun kan an pe o wu iwa to tapa sofin fasiti naa.
- Láti ọdún 2025 lọ, to bá ṣe ìgbọ̀nsẹ̀ sigboro, o rugi oyin - Buhari
- INEC mo ko dé, ẹ̀rí rè é to ṣàfihàn èrú ìbò ní Kogi - Dino Melaye
- Èèmọ̀ rèé o! òkú méjìlá jóná mọ inú mọ́ṣúárì Fásítì OAU
- Àwọn jàndùkú dáná sun Aṣáájú obìnrìn ẹgbẹ́ òṣèlú PDP mọlé ní Kogi
- Goodluck Jonathan jẹ́ olùfọkànsìn àti ìwúrí fún ìrandíran ní Nàìjíríà- Buhari
- Seyi Makinde kò leè gba adé lórí àwa ọba 21, iléẹjọ́ ni yóò là wá níjà - Lekan Balogun
Obinrin to wa ninu fidio yii jẹ akẹkọọ ọlọdun kẹta ni ẹka ẹkọ imọ nipa iṣiro owo, Accountancy, ki wọn to sọ fun un pe ko lọ gbele ẹ.
Fasiti Babcock ni ọmọkunrin to ba ọ́kẹkọbinrin naa lopọ wa ni ile iwosan kan to ti n gba itọju nitori ogun oloro mimu, nibi ti akẹkọọ binrin naa ti lọ ba.
Atẹjade ti fasiti ọhun fi sita tun ṣalaye pe, nigba ti ile iwe naa wa ni isinmi ni akẹkọọbinrin naa lọ ba a nibẹ.












