Dare Adeboye: Ọ̀pọ̀ ọmọ ìjọ RCCG ń ṣèrántí olóògbé Pásítọ̀ náà lẹ́yìn ọdún kan to jáde láyé

Oríṣun àwòrán, @theibim
Leke Adeboye, to jẹ ọmọ alufaa agba ijọ RCCG, E.A. Adeboye ti kọ ọrọ iranti lati ṣaami si ayajọ ọdun kan ti ẹgbọn rẹ, Dare Adeboye jade laye.
Ninu atẹjade kan to fi lede loju opo Instagram rẹ, Leke fi aworan Dare lede pẹlu akọle pe "Iranti ọdun kan pẹlu ifẹ lati ọwọ Leke Adeboye."
Lẹyin naa lo kọ akọle "Titi ayeraye ni o wa ninu ọkan wa."
- Mo ti jíròrò pẹ̀lú àwọn tó yẹ lórí bí mo ṣe maá tún Naijiria ṣe gẹ́gẹ́ bíi Ààre - Kayode Fayemi
- Ìgbà mélòó ló yẹ ko máa pàrọ̀ ‘bedsheet’ rẹ?
- Bí wọ́n ṣe pa Sójà méjì tó ń lọ fún ìgbéyàwó ara wọn ní ìlú
- Amotekun Ondo fi ṣìkùn òfin mú afurasí 37 lórí ẹ̀esùn ìjínigbé, ìdigunjalè àtàwọn ẹ̀sùn míì
- Akọ̀wé Àjọ Iṣọ̀kan, Antonio Guterres ṣàbẹ̀wò sí Naijiria lórí ọ̀wọ́ngógó oúnjẹ̀
- Kí ni ìmọ̀ Sáyẹ́nsì sọ nípa àwọn ènìyàn tó ń bá ajá lòpọ̀? Ìwàdìí ìjìnlẹ̀ rèé
- Ṣé bí ọyàn rẹ ṣe tóbi tàbí kéré tó leè nípa lára ìpèsè omi ọyàn?
- Àwọn afurasí apààyàn pa 'Atiku' ní Ibarapa!
- Akeredolu ṣètò yíyọ owó oṣù òṣìṣẹ́ láti máa gbọ́ bùkátà Amotekun l'Ondo ni - PDP
Dare, to jẹ ọmọ kẹta baba Adeboye ku lọjọ kẹrin, oṣu Karun un, ọdun 2021, niluu Eket, ni ipinlẹ Akwa Ibom, nibi ti oun atawọn ẹbi rẹ n gbe.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post
Oloogbe naa, toun ti iyawo rẹ, Temiloluwa, bi ọmọ mẹta, oun si ni igbakeji oluṣọagutan awọn ọdọ ẹkun naa ṣaaju iku rẹ.
Bi mo ṣe bori ibanujẹ iku ọmọ mi - Adeboye
Lasiko isin "Holy Ghost Service" to waye loṣu to kọja, oluṣọagutan E.A. Adeboye sọrọ nipa bo ṣe bori ibanujẹ iku ọmọ rẹ ọhun.
Gẹgẹ bi ohun ti baba Adeboye sọ, atẹjiṣẹ kan lati ọwọ ọkan lara awọn ọmọ rẹ ninu Oluwa lo tu u ninu lẹyin iṣẹlẹ ọhun.
Ẹni ọgọrin ọdun naa ni oun mọ pe Ọlọrun fẹran oun gidi bo tilẹ jẹ pe oun padanu ọmọ.
Adeboye ni "Nigba ti mo padanu ọmọ mi lọdun 2021, inu mi bajẹ gidi... mo gba atẹjiṣẹ lati ọwọ ọmọ mi kan ninu Oluwa to yi ipo ti mo wa pada."
"Ohun to si fi ranṣẹ si mi naa ni pe Baba, ẹ jẹ ki Ọlọrun gbe yin."
Baba Adeboye ti n tukọ ijọ RCCG bọ lati nnkan bii ogoji ọdun o le diẹ sẹyin.















