2023 Presidency zoning: Shekarau ni káwọn gómìnà Yorùbá yé pariwo ní gbangba nípa ẹni ti ààrẹ kàn

Gomina Shekarau

Oríṣun àwòrán, OTHERS

Gomina Ìpínlẹ̀ Kano tẹ́lẹ̀, Ibrahim Shekarau ti fohùn ránṣẹ́ si awọn gomina Ìpínlẹ̀ mẹtadinlogun tí iha Guusu Naijiria.

O ni pe ki wọn ye ko ẹgbẹ́ jọ láti sọ̀rọ̀ ibẹru lori pe wọn fẹ gba ipo Ààrẹ lọdun 2023.

Shekarau to n ṣojú aarin gbungbun Ìpínlẹ̀ Kano nílé igbimọ aṣofin agba lo sọ èyí lori eto orí amohunmaworan Channels kan.

Nibẹ lo ti ni lẹyin Ààrẹ Muhammadu Buhari, ó yẹ ki Ààrẹ to n bọ lọ́dún 2023 yẹ ko wa lati ẹkùn Guusu lati le jẹ ki jijẹ anfani náà kaari gbogbo ọmọ Naijiria.

Ó tún fi kun un pe ṣe ni ó yẹ ki ẹgbẹ́ òṣèlú APC pin tíkẹẹti ipò Ààrẹ wọn si ọdọ eeyan to dangajia to láti ṣeé ni ẹkùn Guusu fun idibo to n bọ lọ́nà eyi ti ko ju oṣù mejidinlogun lọ mọ bayii.

Àkọlé fídíò, Ebun Oloyede Olaiya Igwe sọ ohun tí ojú rẹ̀ rí lásìkò àìsàn kídìnrín tó yọ ọ́ lẹ́nu

Ẹwẹ, Shekarau sọ oko ọrọ si awọn gomina Guusu pe wọn ń gbimọ pọ láti ja fun ipò Ààrẹ lọ́dún 2023.

Gẹ́gẹ́ bí idibo ọdún 2023 ṣe ń sunmọ, orisirisi akitiyan lọ ti n lọ nínú òṣèlú.

Àkọlé fídíò, Àwọn ọkùnrin tó wà nínú ayé wa gbúdọ̀ bọ̀wọ̀ fún wa - Adarí FIN

Àwọn gomina mẹtadinlogun ìhà Guusu ti pe ipade nígbà méjì ti wọn si n pe fún kí agbára isejoba bọ si apa ọdọ wọn.

Bákan naa ni awọn gomina iha Ariwa mokandinlogun naa ti ṣepàdé lose to kọja.

Àkọlé fídíò, Ọ̀ṣọ́ Aṣọ Òkè ti kọjá lílo ìlẹ̀kẹ̀ níkan

Nibi ti wọn si tako igbese ati ìpinnu awọn akẹgbẹ́ wọn ní Guusu tí wọn ni ẹnikẹni ti ibo rẹ bá pọ ju náà ni yoo di Ààrẹ nínú ètò idibo to n bọ.

Lórí ètò náà, Shekarau ni ó ṣe ni laanu pé ọrọ a ń to ó, a ó to o ti wa sọ ìjọba awarawa di kíkóra jọ ni ẹlẹkun n jẹkun.

Torí èyí, Shekarau bu ẹnu atẹ lu oniruuru ipade àwọn gomina Guusu to sì ni kí wọn jawọ ninu kíkọ awọn ẹgbẹ́ mii lórílẹ̀èdè lati ṣe iru nkan táwọn naa n ṣe.

Ó ni ó yẹ ki wọn ba ara wọn sọ̀rọ̀ laarin ẹgbẹ́ ju ki wọn maa pariwo ni gbangba.

Àkọlé fídíò, 'Ìyà Muinat kú nígbà tó ń mu ọmú lọ́wọ́ ni èmí ìyà-ìyá rẹ̀ ń tọ́jú rẹ̀ kí ògiri kíláàsì tó wó pa á'

Òun ni tìrẹ ni bo tilẹ̀ jẹ́ pé òun gba pe èèyàn to dangajia lọ yẹ kó jawe olubori, òun sì gba pe ki wọn jẹ ko kari ni Naijiria

"àmọ́ ibi tí mo kan ti lodi si awọn gomina iha Guusu ni kikora jọ láti máa sọ pé dandan awọn lo kan.

Mo lérò pé ọrọ àárín òṣèlú lo yẹ ki eleyii jẹ."

Àkọlé fídíò, Ọ̀wọ́ ọ̀tún Ọlọ́run Olódùmarè ni Ogboni máa wà bí ó bá re ibi àgbà ń rè