Àwọn ìgba mẹ́rin t'áwọn èèkàn tí dùbúlẹ̀ àìsàn lásìkò tí wọ́n ń jẹ́jọ́ níwájú adájọ́

Oríṣun àwòrán, other
Ọga agba ile isẹ to n risi owo awọn osisẹfẹyinti tẹlẹri, Abdurasheed Maina, ti darapọ mọ awọn eeyan to daku nile ẹjọ lẹyin ti wọn fi ẹsun ikowojẹ kan wọn.
Ọjọ kẹwaa, loṣu Kejila, ọdun 2020 ni Maina daku rangbọdan nile ẹjọ lẹyin ti ile ẹjọ pada bẹrẹ si n gbọ ẹsun ti wọn fi kan pe o lu biliọnu meji naira ni ponpo.
Pupọ ninu awọn ọmọ Naijiria lo ti n sọ pe oun ti Main ṣe kii ṣe tuntun nitori awọn eeyan kan ti wọn fi iru ẹsun bẹẹ kan ti daku bẹẹ ṣaaju akoko yii.
- Wo ìgbéyàwó olówó iyebíye tí awakọ̀ Kabúkabú ti jẹ̀bùn ọkọ N3.4m
- Wo ohun tí yóò ṣẹlẹ́ tí wọ́n bá jí ọpa àṣẹ gbé nílé àṣòfin
- Ìlú méjì kọjú ìjà síra wọn l‘Ondo torí aáwọ̀ ilẹ̀, ọba kan wà ní ‘Coma’, èkejì fo ògiri jáde
- Ọmọ Naijiria hú ẹ̀sùn ìfipá bánilòpọ̀ tí wọ́n fi kan Fatoyinbo síta lẹ́yìn tó lọ sí Shiloh
Wo diẹ lara awọn eeyan to ti daku bii Maina, tabi to dede dubulẹ aisan lẹyin ti wọn fẹsun ikowojẹ kan wọn.
Dino Melaye
Dino jẹ ọkan gboogi lara awọn oloṣelu to ni idan lọwọ ni Naijiria nitori ko ṣeni to le sọ iru aṣa ti o le ti ọwọ rẹ jade.

Oríṣun àwòrán, @sumner_sambo
Ni oṣu Kẹrin, ọdun 2018 ni Melaye dede fo kuro ninu ọkọ to wa lori ere, eyii ti wọn fi n gbe lọ lati koju ẹsun kan ti wọn fi kan.
- Ìwọ́de ńlá yóò bẹ́rẹ̀ lọ́jọ́ táwọn gómìnà bá yá ₦17trn nínú owó ìfẹ̀yìntì òṣìṣẹ́ - NLC
- Ìdí rèé tí mo fi yan ikọ̀ PMS rọ́pò NURTW nípìnlẹ̀ Oyo - Seyi Makinde
- "Buhari, Olóṣèlú àtàwọn òjíṣẹ́ Ọlọ́run ló mú àjẹbánu gogò ní Nàíjíríà"
- Ooni Adeyeye ti Ile Ife fẹ sèrànwọ́ owó iléèwè fún akẹ́kọ̀ọ́ 5 mílíọ̀nù ní Nàìjíríà
Igba to di ọjọ kẹrin, oṣu Kinni, ọdun 2019 ni Melaye fa ara rẹ ileeṣẹ ọlọpaa lọwọ lẹyin ọjọ meje ti wọn ti wa lẹnu ọna ile rẹ.
Lẹyin iṣẹju diẹ to jọwọ ara rẹ fun awọn agbofinro tan lo dede ṣubu lulẹ, ti ko si le rin mọ.
Ṣugbọn lẹyin ti wọn gbẹ lọ si ọọfisi lo tun ṣubu lẹẹkeji, to si n mi gulegule bi ẹni ẹmi fẹ bọ lẹnu rẹ..
- Ọkùnrin kan rí ẹ̀wọn he lẹ́yìn tó lu obìnrin ní jìbitì ìfẹ́ tí iye rẹ̀ tó $15,000 lórí ayélujára
- Fr Mbaka, ọmọ ìjọ rẹ̀ kọ̀lu akọ̀ròyìn BBC, wọ́n lù wọ́n ní àlùdojúbolẹ̀
- Háà! Àgbo tí mò ń lò láti jò kó bá mi, ìdí mi ti yọ́ tán - Nkechi Blessing figbe ta
- Ọlọ́pàá tún yìnbọn pa awakọ̀ Márúwá, ìwọ́de gba Portharcourt kan
Olisa Metuh
Ni ọdun 2018 kan naa ni wọn gbe Olisah Metuh to jẹ alukoro tẹlẹ fun gbẹ oṣelu PDP.

Oríṣun àwòrán, other
Ajọ EFCC gbe Olisah Metuh lọ sile ẹjọ giga kan nilu Abuja fun gbigba irinwo miliọnu naira lọwọ ọfiisi alamojuto abo lorilẹede Naijiria lọdun 2014.
Nigba ti yoo fi wa si igbẹjọ nileẹjọ, gbalaja bayii ni Metuh sun sori bẹẹdi alaarẹ, Stretcher wa si ile ẹjọ.
Kemebradikumo Pondei

Oríṣun àwòrán, NDDC
Oṣu Keje ọdun 2020 ni adele Ọga Agba ajọ to n mojuto idagbasoke agbegbe Niger Delta, Ọjọgbọn Kemebradikumo Pondei, daku rangbọndan lasiko ti iwadii ẹsun bi wọn ṣe na owo ajọ NDDC labẹ rẹ n waye.
Pondei daku lasiko to n ṣalaye iye owo ti ajọ NDDC na labẹ iṣakoso rẹ.

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Niṣe ni gbogbo awọn to wa nibi ijoko naa n sare kijokijo lasiko ti Ọjọgbọn Pondei daku lori aga to joko si.
Eyi si mu ki gbogbo awọn to tẹle e wa sibẹ o ma a fẹ ẹ l'oju, fẹ ẹ nimu, rọ omi si i l'ori ko ma baa gba bẹ lọ.
Haliru Bello
Haliru, to jẹ alagba ẹgbẹ oṣelu PDP tẹlẹ ni ajọ EFCC fẹsun mẹrin to jọ mọ didari owo ijọba si apo ara rẹ kan lọdun 2015.
Nigba ti alaga naa yoo wa siwaju ilke ẹjọ, inu aga awọn abarapa ti ko le rin lo ti wa sile ẹjọ.
Maj. Gen. Hakeem Otiki
Inu aga arọ ti ko lẹsẹ naa ni ọgagun Hakeem Otiki ti wa sile ẹjọ awọn ologun lọdun 2020.

Oríṣun àwòrán, @Chikelinks
Wọn fẹsun kan ọgagun naa pe o ko owo awọn ọmọ marun un to salọ sapo ara rẹ lọdun 2019.
Lẹyinorẹyin, ile ẹjọ naa ni ki wọn rẹ ipo rẹ silẹ lati Major General si Brigadier General, ki wọn si tun fi ọwọ osi juwe ile fun.
Owo ti wọn ni o lu ni ponpo ko ni din ni irinwo miliọnu naira.












