Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ àwọn méji tó jẹ ẹran ara ọlọ́pàá tí wọ́n pa n'Ibadan

Awọn afuruasi

Oríṣun àwòrán, others

Ẹran ara ọlọ́pàá di èkìrí ẹran súyà, wo àwọn tó jẹ́ níbẹ́.

Awọn ọlọpaa ni ipinlẹ Oyo ti mu awon meji ti wọn ni wọn fẹsun kan pe wọn n sunẹran ọlọpaa jẹ lasiko iwọde #EndSARS to kọja.

Alukoro ileṣẹ ọlọpaa ni ipinlẹ Ọyọ, SO Olugbenga Fadeyi ti salaye fawọn akọroyin pe lootọ ni o.

Awọn afunrasi mejeeji naa oloyun ọmọ ọdun mẹrinlelọgbọn kan pẹlu arakunrin ẹni ọdun mẹtalelogoji ọhun ti n turabayii nileeṣẹ ọlọpaa ọtẹlẹmuyẹ nilu Abuja.

Alaboyun naa la gbo pe o jẹ ẹran ara ọlopaa kan ṣugbọn to ni iọ ni wọn pa mọ oun. Amọṣa, ọgangan ibi ti iṣẹlẹ naa ti waye ni wọn ti mu.

O ni arakunrin ẹni ọdun mẹtalelogoji naa lo fun oun pe ki oun fi si ipamọ.

Àkọlé fídíò, Oba Adedokun Abolarin ti Oke Ila: Ó ya ọ̀pọ̀ tó súnmọ́ mi lẹ́nu bí mo ṣe ń kọ́

Bi o tilẹ jẹ pe arakunrin naa ko sẹ pe oun ko si pẹlu awọn janduku miran nibi ti iṣẹlẹ naa ti waye.

Ṣugbọn arabinrin aboyun naa lo funra rẹ bu ekiri ẹran ati pe aṣọ inuwọ lasan lo kan beere lowo oun lati fi yi wọn pamọ.

Awọn ọlọpaa

Oríṣun àwòrán, others

Awọn Ọlọpaa ti wọn sọ ara wọn di ẹran ijẹ naa wa lara awọn ọlọpaa ti wọn da sita lati lọ pana wahala iwọde #EndSARS.

End Sars yii to waye lọjọ kejilelogun, oṣu kẹwaa, ọdun 2020, nbẹ ni wọn ti kagbako iku gbigbona naa

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Aṣa lori BBC:Wo ìrúfẹ́ ìgbeyàwó méje tó wà nílẹ̀ Yorùbá àti ojúṣe Alárinà