Coronavirus in Nigeria: Àjọ NBS ní covid-19 ló fa ọ̀wọ́ngógó oúnjẹ ní ìpínlẹ̀ Eko, Kano, Rivers àti Abuja

Market

Oríṣun àwòrán, others

Laisi ani ani, ajakalẹ arun coronavirus ti da ọwọngogo ounjẹ silẹ nipinlẹ Eko, Kano, Rivers ati Abuja.

Ajọ National Bureau of Statistics to n ri akọsilẹ ohun to n ṣẹlẹ ní Naijiria lo f'ọrọ naa lede.

Ajọ NBS sọrọ naa ninu iroyin to fi sita lori ipa ti aarun onigbameji ti ni nipinlẹ Kano, Eko, Rivers ati Abuja.

Ajọ NBS ni ọwọngogo ounjẹ buru jai lawọn nipinlẹ mẹrin wọnyii, amọ awọn eeyan ipinlẹ Rivers ati Abuja ko tii ri nkan nkan.

Ida mejilelaadọrin ninu ọgọrun idile lawọn ipinlẹ naa lo sọ pe awọn ko ri ọwọ mu lọ sẹnu mọ daadaa.

Atẹjade NBS fihan pe ọrọ aje awọn olugbe ipinlẹ mẹrẹẹrin naa dẹnu kọ lẹ laarin oṣu kẹfa si ekeje.

NBS sọ pe afaimọ ki iyan ma bẹ silẹ ni Naijiria nitori awọn mẹkunnu ti n ke wi pe awọn ko rowo ra ounjẹ mọ.

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Aṣa lori BBC: Mọ̀ si nípa oríṣìí ẹ̀ka ìsọ̀rí ọ̀rọ̀ àti ìwúlò wọn