Constitution Review: Afenifere rọ àwọn aṣòfin láti lo àbá 2014 CONFAB fún àtúnṣe ìwé òfin Nàìjíríà

Oríṣun àwòrán, @ngoamazing2009
Ẹgbẹ ajijagbara ilẹ Yoruba, Afenifere ti rọ ile aṣofin agba l'Abuja lati lo aba to jẹyọ nibi apero CONFAB to waye lọdun 2014 fun atunṣe iwe ofin orile-ede Naijiria.
Ẹgbẹ Afenifere, to duro lori pe atunto orile-ede yii ni ojutu si iṣoro to n koju Naijiria, sọrọ yii lẹyin ipade awọn olori ẹgbẹ naa lọjọ Aje labẹ alaṣẹ Oloye Reuben Fasoranti.
Ninu atẹjade kan ti akọwe ẹgbẹ naa, Yinka Odumakin fi sita, ẹgbẹ Afenifere ni awọn gbawọn aṣofin lamọran yii lẹyin ti wọn ranṣẹ si awọn lati kopa ninu eto atunṣe iwe ofin Naijiria ti ọdun 1999 ti a n lo lọwọ.
Afenifere ni igbesẹ lati ṣe atunṣe iwe ofin Naijiria ti di ohun ti ijọba n kede lọdun mẹrin mẹrin lai si iyipada kankan to ba ofin ọhun.
Ẹgbẹ Afenifere ni yoo jẹ nkan to buru jai ti ijọba ba tun gunle eto atunṣe iwe ofin Naijiria lasiko yii lai ṣe amulo awọn eleyi to ti waye tẹlẹ.
Afenifere sọ pe titẹle awọn aba to jẹyọ nibi apero CONFAB ọdun 2014 nipa ijọba awaarawa lo le mu ilọsiwaju ba Naijiria.
- Bí mo bá wọlé padà, mí ò lè yàn Ize Iyamu tàbí Osagiobare sípò olùbádámọ́ràn- Obaseki
- Olórin Kano tí wọ́n dájọ́ ikú fún pe ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Kogi kéde ọjọ́ ìwọlé àwọn akẹ́kọ̀ọ́ padà sí iléèwé
- Tinubu, yé é sọ̀rọ̀ abẹ́lẹ̀, bọ́ sí gbangba láti bèèrè àtúntò Nàíjíríà lọ́dọ̀ Buhari - Afẹnifẹrẹ
Afenifere tun bu ẹnu atẹ lu afikun owo ina ati epo bentiroolu ti ijọba kede laipẹ yìí.
Bakan naa ni ẹgbẹ naa tun tako igbesẹ ile igbimọ aṣoju-ṣofin l'Abuja lati jiroro lori aba ti yoo fun ijọba apapọ lagbara lori alumọọni inu omi kaakiri orile-ede Naijiria.
- Ọmọ Ààrẹ lẹ́tọ̀ọ́ láti ṣe ìgbéyàwó yálà àwọn ará ìlú fẹ́ràn ìjọba bàbá rẹ̀ tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́ - Aisha Buhari
- Ó yẹ kí Buhari dá owó epo padà sí ₦97 tàbí kó kọ̀wé fipò sílẹ̀ - Àwọn akẹ́kọ̀ọ́
- Owó lítà epo ní Nàíjíríà ló kéré jùlọ l‘Áfíríkà - Lai Muhammed
- Ìjà ẹgbẹ́ òṣèré TAMPAN àti ANTP ni kò jẹ́ kí wọ́n pe Baba Legba sínú eré mọ́, kó tó kú - Owolabi Ajasa
- Wo ọ̀nà ìsanwó tuntun fún àwọn oníbárà iná mọ̀nàmọ́ná ní Eko (EKDC)















