Obadiah Mailafia: DSS ti fi igbákejì gómìnà CBN tó ní gómìnà kan ní Àríwá Naijiria ní Ọ̀gá Boko Haram sílẹ̀

Oríṣun àwòrán, FACEBOOK/OBADIAH MAILAFIA
Igbakeji Gomina Banki Apapọ Naijiria (CBN) tẹlẹri, Obadiah Mailafia ti ni oun ko mọ wi pe wọn ka ohun oun silẹ lasiko ti oun ṣe ifọrọwanilẹnuwo pẹlu ileeṣẹ redio.
Mailafia sọ eyi lasiko to n ba BBC sọrọ lẹyin ti Ajọ ọtẹlẹmuyẹ DSS fi silẹ lẹyin ifọrọwanilẹnuwo.
O ni awọn Fulani meji ni wọn ri oun ti wọn si bẹrẹ si sọ gbogbo ohun to n ṣẹlẹ ninu ikọ Boko Haram fun oun nitori oun gbọ ede ti wọn n sọ.
- Victor Agunbiade ni ojú àlá ni Ọlọrun ti yan iṣẹ́ ọmọ ogun ojú omi fún òun ní America
- Ilé ayé mi ti d'ojú bolẹ̀ pẹ̀lú ikú àfẹ́sọ́nà mi- àfẹ́sọ́nà Immaculate Okochu
- Àgbo Covid-19 Madagascar kò ṣiṣẹ́, àwọn ènìyàn tí bẹ̀rẹ̀ sí ní kú níbẹ̀
- Ilé ẹjọ́ ju ọmọ ìjọ tó fi ìpá bá ọmọ pásítọ̀ rẹ̀ sùn ní ìpínlẹ̀ Ondo sí ẹ̀wọ̀n gbére
- Wo ọ̀nà márùn ún tí o lè gbà dáàbò bò ara rẹ lọ́wọ́ ìjàmbá láì gbé ìbọn!
Igbakeji Gomina Banki Apapọ Naijiria (CBN) tẹlẹri, Obadiah Mailafia ni ajọ DSS ko kan an nipa fun oun lati sọ ohun ti oju oun kori.
Mailafia fikun pe awọn oṣiṣẹ ajọ DSS wuwa ọmọluwabi si oun, ti wọn ko si fi iya jẹ oun lasiko ifọrọwanilẹnuwo naa.
Bakan naa ni Mailafia ni oun fẹran Aarẹ Buhari ati wi pe oun ṣe agbatẹru fun un, amọ awọn to wa ni iṣejọba rẹ ko fun aarẹ ni atilẹyin to nilo lati mu idagbasoke ba orilẹede Naijiria.
- Èèyàn 373 ni ààrùn coronavirus tún ṣẹ̀ṣẹ̀ ràn ní Nàìjíríà - NCDC
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Osun tí búwọlù ìlànà àyẹyẹ Ọṣun-Oṣogboo ọdún 2020
- Wo díẹ̀ nípa ohun tí Walter Carrington gbé ṣe nígbà ayé rẹ̀
- ‘Àwọn òlóṣèlú kò ní ìwà ọmọlúwàbí ló jẹ́ kí wọ́n má a lọ láti ẹgbẹ́ òṣèlú kan lọ sí òmìràn’
- Ogun Àgbẹ́kọ̀yà, ẹ̀kọ́ wo ló yẹ́ kí àwá ọ̀dọ́ kọ́ níbẹ̀?
DSS ti fi igbákejì gómìnà CBN tó ní gómìnà kan ní Àríwá Naijiria ní Ọ̀gá Boko Haram silẹ
Ileeṣẹ otẹlẹmuyẹ lorilẹede Naijiria, DSS ti fi silẹ lẹyin ẹsun to fi kan gomina kan ni ẹkun ariwa Naijiria.
- "A ti ń sin òkú méjì sínú ibójì kan náà nítorí ọ̀wọ́ngógó ibojì ìsìnkú"
- Wo díẹ̀ nípa ohun tí Walter Carrington gbé ṣe nígbà ayé rẹ̀
- Ẹgbẹgbẹ̀rún ọmọ Nàìjíríà ní yóò má a kú lójoojúmọ́ tí wọn bá gbà wọ́n láàyè láti gbébọn dání- Amofin
- Ilé ẹjọ́ ju ọmọ ìjọ tó fi ìpá bá ọmọ pásítọ̀ rẹ̀ sùn ní ìpínlẹ̀ Ondo sí ẹ̀wọ̀n gbére
- Ooni Ifẹ bu ẹnu ẹ̀tẹ́ lú ètò BBNaija nítorí ó tàbùkù àsà Yoruba
Obadiah Mailafia lo sọ lori redio pe gomina ni ẹkun ariwa Naijiria gan an ni ọkan gboogi lara awọn adari ikọ agbesunmọmi Boko Haram ni Naijiria.
O ni awọn ikọ Boko Haram to ti fẹhinti lo tu asiri naa si oun lọwọ.
Ilẹẹṣẹ DSS gbe e lẹyin ti iroyin naa kaakiri ayelujara ti wọn si fi ọrọ wa a lẹnu wo.
Obadiah wọ ọgba DSS lọ lati lọ wi ti ẹnu rẹ pẹlu awọn agbẹjọro rẹ meji ti orukọ wọn n jẹ Pius Akubo (SAN) ati Yakubu Bawa.
Amọ, lẹyin wakati mẹfa ni wọn fi silẹ, ti awọn ikọ afẹhọnuhan to jẹ alatilẹyin rẹ ko si kuro nibẹ titi ti wọn fi fi silẹ.













