Alaafin: Olori Aanu Adeyemi aya Oba Lamidi Adeyemi ti ìlú Oyo ní ohun tó bá kúkú wu ọmọ láti jẹ kìí...

Àkọlé fídíò, Alaafin: Olori Aanu Adeyemi ṣàlàyé ìdí tó ṣe gẹ́ Oba Lamidi Adeyemi ti ìlú Oyo

Gbogbo ohun ti mo fẹ́ ni mo n ri laafin Oba Lamidi Adeyemi- Olori Aanu

Ohun to wu mi ko wu ọ ni ọrọ Ayaba Aanuoluwapọ Adenike Adeyemi nigb ati BBC kan si Aafin Kabiesi ni ilu Oyo.

Olori yi wa lara awọn Olori to kere julọ ni aafin ti ọpọ maa n pe ni òló ẹlẹjẹ tutu ti Baba fi n mi lasiko yii.

O jẹ ọmọ ipinlẹ Osun (Ile Ife ati Ede) o si gbe ni ilu Ibadan dagba.

Olori Aanu ṣi n kawe lọwọ ni fasiti ọlọgba ẹranko nibi ti sanmọnti gbe dunlẹ ni ilu Ibadan UI nibi to ti n kọ imọ ijinlẹ nipa oṣelu.

Olori atawọn ọmọ ori Ade ti Oba oke fun un
Àkọlé àwòrán, Awọn ogo ọmọ ti Oba oke yọnda fun Olori ati Alaafin

Olori Aanu ṣalaye pe oun pinnu pe oun gbọdọ ni ifọkanbalẹ nile ọkọ lo jẹ ki oun fẹ Alaafin ti ọpọ maa n sọ pe o ti dagba ju oun lọ pupọ ju.

Olori
Àkọlé àwòrán, Olori Aanu tu kẹké ijo laafin olowo ori ẹ

Olori Aanu ṣalaye fun BBC gbogbo nkan to wu oun ti ọkan oun n fẹ ni Alaafin n pese fun oun ati pe gbogbo olori ni Oba fẹ ki wọn kawe lo ṣe n ran gbogbo wọn nile iwe.

Olori
Àkọlé àwòrán, Orekelewa Ayaba

Olori ni ooreọfẹ Olorun loun n jẹ laafin.

O sọrọ lori ajọṣepọ awọn olori keekeeke ati agba pe ibọwọfagba ati irẹlẹ ni oun n kọ sii lojoojumọ ni aafin.

Olori Adenikẹ tun sọ nipa ẹkọ asa ati iṣe ati oriki ti oun ti gba ni aafin ati pe oun yoo fi kọwe nipa eto idajọ Alaafin lọjo ọla.

Awon olori ati Baba
Àkọlé àwòrán, Ninu awọn olori Kabiesi

Olori ni onikaluku lo mọ idi to fi fẹ ọkọ rẹ ati pe oun ko kabamọ pe oun fẹ Kabiesi.

Ohun to ba wu kaluku ni ko fi ẹnu rẹ sọ lori ayelujara.