You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Chrisland Student Sex Video: Olùkọ́ mẹ́rin fojú balé ẹjọ́ lórí ẹ̀sùn ìbálòpọ̀
Awọn olukọ mẹrin nile ẹkọ Chrisland Schools to ba awọn akẹkọọ ile ẹkọ naa lọ siluu Dubai fun eto World School Games ti foju bale ẹjọ majisttreeti to wa ni Yaba, niluu Eko.
Orukọ awọn olukọ naa ni Oladotun Sotunde, Elesho Tajudeen, Rhoda Olanipekun ati Ajiboye Hammed.
Awọn eeyan naa n koju ẹsun igbimọpọ lati da omi alaafia ilu ru, eyii ti ileeṣẹ ọlọpaa fi kan wọn.
Ṣaaju ni ijọba ipinlẹ Eko ti kọkọ paṣẹ ki wọn gbe gbogbo ẹka ile ẹkọ Christland College to wa l'Eko ti pa lẹyin ti fidio ibalopọ awọn akẹkọọ ile ẹkọ naa ni Duabai fa oju opo Twitter ya.
Amọ ijọba ṣi ile ẹkọ naa pada lẹyin iwadii iṣẹlẹ ọhun.
Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ Uche Igwe di èrò iléẹjọ́ lórí ẹ̀sùn pínpín fídíò ìbálòpọ̀ ọmọdé
Magisreti Adeola Adedayo wa gba beeli rẹ ni iye owo to to miliọnu mẹwaa Naira ati oniduro mẹta.
Sọrọsọrọ Uche Igwe ti yọju si ileẹjọ lori ẹsun pe o ṣe atunpin fidio ibalopọ ọmọ ọdun mẹwaa lori ẹrọ ikansiraẹni, Twitter.
Fidio ọmọ ọdun mẹwa ni ileẹkọ Chrisland ni agbegbe Lekki, nipinlẹ Eko to n ba akẹgbẹ rẹ ni ibalọpọ ni sọrọsọrọ naa ṣe atunpin rẹ lori ẹrọ Twitter.
- Báwo ni ọ̀rọ̀ ilé ṣe fa Gbas-gbos láàrín Mercy Aigbe, ìyáále rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀?
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Eko ṣí gbogbo ẹ̀ka ilé ẹ̀kọ́ Chrisland padà
- Ìjọba Eko ti iléẹ̀kọ́ Chrisland pa torí ẹ̀sùn ìbálòpọ̀ láàrín àwọn àkẹ́kọ̀ọ́
- Kìí ṣe ẹ̀bi wa wí pé àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ṣe àṣemáṣe - ile ẹ̀kọ́ Chrisland
- Fídíò Chrisland, ikú Sylvester Oromoni, àtàwọn ìṣẹ̀lẹ̀ gbankọ gbì tó wáyé láwọn ilẹ ẹ̀kọ́ girama
- Wo bí o ṣe lè so fóònù rẹ pọ̀ mọ́ àwọn ǹkan tí ọmọ rẹ ń wò lórí fóònù rẹ̀
- Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ Uche Igwe di èrò iléẹjọ́ lórí ẹ̀sùn pínpín fídíò ìbálòpọ̀ ọmọdé
Igwe to n gbe ni agbegbe Ikorodu nipinlẹ Eko ni ileẹjọ fi ẹsun oniga meji kan.
Ẹsun naa ni titẹ oju ofin to de alaafia ilu mọlẹ ati idunkokomọni lori ayelujara.
Agbẹjoro fun ijọba ni ileeṣẹ ọlọpaa ni Panti, nipinlẹ Eko, Augustine Nwabuisi ni Igwe ṣe atunpin fidio naa pẹlu imọ rẹ ni kii ṣe aṣiṣe.
Ẹsun onigun meji ni ijọba fi kan an
Igwe lo oju opo Twitter rẹ gangan lati pin fidio naa kaakiri ẹrọ ayelujara lai gba aṣẹ ileẹkọ tabi lọwọ obi awọn ọmọ naa.
Ijọba ni Ọjọ Kejidinlogun, Oṣu Kẹrin, ọdun 2022 ni sọrọsọrọ naa ṣe aṣemaṣe ọhun.
Ihuwasi naa tako ofin ipinlẹ Eko to de ihuwasi awọn eniyan lori ẹrọ ayelujara ati iwa ọdaran ni ipinlẹ Eko.
Amọ sọrọsọrọ naa ni oun ko jẹbi ẹsun ti wọn fi kan oun.
Magisreti Adeola Adedayo wa gba beeli rẹ ni iye owo to to miliọnu mẹwa Naira ati oniduro mẹta.
- Kọ́ńdọ̀ọ̀mù méjìlá lá rí ní iyàrá ilé ìtura tí wọ́n ti fípa bá arábìnrin Ulochi lòpọ̀- Olọ́pàá
- Èmi ò gbé'ṣẹ́ rán ẹnikẹ́ni láti ra fọ́ọ̀mù ìdíje ààrẹ fún mi o, ẹ máà kóbá mi -Ààrẹ tẹ́lẹ̀ Goodluck Jonathan fún Miyetti Allah lésì
- Ìpapòda Aláàfin kò ní dá ètò ìfinijoyè Gbajabiamila dúró- Ọyọmesi
- Ó pé ọdún 35 tí Obafemi Awolowo kú, wo àwọn nkan mánigbàgbé tí o kò gbọ́ rí nípa rẹ̀
- INEC lẹ́tọ̀ọ́ láti bẹ́gi dínà èróngbà Emefiele láti díje du ipò Ààrẹ- Ilé ẹjọ́
- Irọ́ ni, irọ́ kọ́ Toyin Adegbola àti àwọn míì sọ̀rọ̀ nípa fídíò Biola àti Olùdarí ere tí wọ́n jọ ní gbólóhùn asọ̀
- Wo àwọn òjé tí àwọn olóṣèlú máa fi ń jẹ àwọn ènìyàn bí ètò ìdìbò bá ti ń súnmọ́lé