You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Osun ti mú ọlọ́dẹ tó yìnbọn pa ìmàámù dípò ẹran ẹtu
Ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Osun ti mu arakunrin kan to jẹ ọdẹ apẹran, ti wọn lo pa baba agba ẹni ọdun mejidinlọgọrin nijọba ibilẹ Aiyedaade.
Wọn fi ẹsun kan Sulaimon Jimoh pe o pa imaamu abule Alaguntan, nilu Orile Owu, Ọgbẹni Adegun Yusuf lọjọ kẹtadinlogun, oṣu Kẹrin, ọdun 2022.
Gẹgẹ bi iroyin ti Nigerian Tribune gbe jade, Ọgbẹni Jimoh sọ fun awọn ọlọpaa pe ẹran Ẹtu ni oun ri lasiko ti oun n ṣe ọdẹ ninu igbo.
Ti oun si yinbọn mọ lati ọ̀ọ́kán. Amọ iyalẹnu lo jẹ nigba ti oun sunmọ ẹranko ti oun pa lati gbe, ti oun si ba oku baba agba naa dipo ẹran Ẹtu.
- Ọlọ́pàá Eko kéde orúkọ ọlọ́pàá tó ṣíná ìbọn bolẹ̀ nílé ọtí, téèyàn méjì fi kú
- Èèyàn bí méjì kú, ọ̀pọ̀ farapa lásìkò tí àwọn afurasí ọmọ Auxiliary àti Isota kọlu ara wọn ní Ibadan
- Èsì àyẹ̀wò ohun tó ṣekú pa gbajúmọ̀ akọrin ẹ̀mí, Osinachi Nwachukwu ti jáde
- Àwọn ológun pa ikọ̀ Boko Haram ogún, wọ́n dóòlà àwọn obìnrin tó wà ní ìgbèkùn
- Lukman gbẹ̀yín ẹbí lọ bẹ́ orí ìkókó ti wọ́n sìn ní Abeokuta, àṣírí tú bó ṣe fẹ́ tàá
- Wọ́n ti ṣe ìsìnkú àpapọ̀ fún èèyàn 50 lára àwọn tó jóná níbúdò ìfọpo tó gbiná ní Imo
- Mọ̀ nípa Baṣọ̀run ìlú Oyo, Oloye Yusuf Akinade Ayoola tí yóò delé de Aláàfin tuntun
Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Osun, Yemisi Opalola sọ pe ọmọ baba naa lo fi ẹjọ sun ni agọ ọlọpaa, ti ọwọ fi tẹ afurasi naa.
Gẹgẹ bo sẹ sọ, o ni abule Alaguntan ni arakunrin ọlọde naa ati oloogbe n gbe.
Opalola sọ pe ni kete ti iwadii ba pari ni wọn o gbe afurasi naa lọ si ile ẹjọ.
Iru iṣẹlẹ yii ti waye ri nipinlẹ Ondo
Ninu oṣu Kejila, ọdun 2021, ni ọwọ ọlọpaa tẹ arakunrin ọlọdẹ kan, Ismaila Ojo, ti wọn lo pa ara abule Ita-Merin, nitosi ilu Ọrẹ.
Iroyin sọ pe Arakunrin Ismaila Ojo, yinbọb pa alamuleti rẹ to jẹ ẹni aadọrin ọdun, nibi ti onithun ti n ṣe igbọnsẹ ninu igbo to wa lẹyin ile wọn.
Ṣugbọn ninu ọrọ to sọ, ọlọde naa, Ojo, sọ fun awọn ọlọpaa pe oun n dan ibọn oun wo ni ni bi aago mẹta oru ọjọ naa.
O ni ẹranko ni oun ri, ti oun si yinmọ mọ.
Amọ baba agba naa ni oun ba ninu agbara ẹjẹ, nigba ti oun fẹ ẹ gbe ẹran ti oun pa.
Lẹyin ọjọ diẹ ni baba naa ku si ileewosan.