Wo bí inú ààfin tuntun ìlú Ibadan ṣe rí àti àwọn ọ̀nà tí kíkọ́ rẹ̀ gbà wáyé
Láti ọdún 1993, láyé Olubadan Yesufu Oloyede Asanike ni Olubadan ti rí ààfin tó jẹ́ ti ìlú lò gbẹ̀yìn.
Ìdí nìyí tí ìgbìmọ̀ àwọn ọmọ bíbí ìlú Ibadan fi dìde láti wá wọ̀rọ̀kọ̀ fí ṣàdá, tí wọ́n sì sáré káàkiri láti kọ́ ààfin tó jojú ní gbèsè fún oyè Olubadan.
Ninu ọrọ to ba BBC sọ, Aarẹ agba ẹgbẹ ọmọ bibi ilu Ibadan, CCII Amofin Wọle Ajewọle ṣe alaye lori ohun to pilẹ aini aafin ilẹ Ibadan lati igba ipilẹ wa, ohun to ṣokunfa kikọ aafin akọkọ ati idi ti wọn fi pa aafin akọkọ naa ti.
- Àwọn egúngún tó jẹ́ mánigbàgbé nínú àṣà àti ìṣẹ̀ṣe ilẹ̀ Ibadan
- Gómìnà Seyi Makinde buwọ́lu ìyànsípò Olakunleyin gẹ́gẹ́ bíi Olubadan
- Ìgbé ayé Mufu Olóòṣà-oko, ọmọ ìta tó kú ikú ọlọ́ṣà
- Ibadan Oloolu Masquerade: Ojúmitó kan ní ìbọn kò ran Oloolu àmọ́ ọpẹ́ ọlọ́pàá tó kojú jàǹdùkú, ọ̀rọ̀ kò bá bẹ́yìn yọ
- Kiriji war (1877-1893), Ibadan, Ekiti, Ijesa: Ìkónilẹ́rú ilẹ̀ Yorùbá ló parí Ogun Kiriji
Bakan naa lo ṣalaye bi wọn ṣe bẹrẹ kikọ aafin tuntun yii ati awọn ipenija ti wọn koju.
Amofin Ajewọle ni aini aafin Ibadan lati iwasẹ ko ṣẹyin bo ṣe jẹ pe jagunjagun lo tẹ ilu Ibadan do ni. O ni ile olukaluku to jẹ Baalẹ ni wọn to lo.
- Eji Gbadero: Ó pa Raji Oba nítorí ilẹ̀ nìjọba bá yẹgi fún un
- Adebisi Idikan: Òun ló gba Ìbàdàn sílẹ̀ lọ́wọ́ ìyà owó orí sísan
- Itan Manigbagbe: Oba Asanike Yefusu Oloyede, Olubadan tó gbóyà, aláwàdà, tó tún kún fún ọgbọ́n
- Popular areas in Ibadan: Àwọn àdúgbò tó gbajúmọ̀ jùlọ nílùú Ibadan rèé àtàwọn nǹkan tó yẹ kí o mọ̀ nípa wọn
O ni igba to ya ni wọn ko ara jọ pe ki wọn kọ aafin, eleyi ni wọn si kọ si agbegbe Ọjaaba nilu Ibadan nitori pe aaringbungbun ilẹ Ibadan ni wọn fẹ ko wa nigba naa. Amọṣa o ni aisi aaye pupọ nibẹ jẹ idiwọ fun Ọba Ashankẹ to jẹ nigba naa, to si ṣe okunfa bi awọn ọba to tẹle ṣe yẹra fun lilo aafin naa.







