Sunday Igboho: Ariwò tí ẹ̀ ń pa, kò lè dóòlà ẹ̀mí Sunday Igboho, kò le è sá mọ́ ìjọba lọ́wọ́ - Oba Adekunle Oyelude

Sunday Igboho

Oríṣun àwòrán, sunday_igboho1

Ọba Olowu ti Kuta, nipinlẹ Osun, Hammed Adekunle Oyelude Makama ti ni ijiroro nikan lo le e gba Sunday Igboho silẹ ni ọwọ ijọba orilẹede Naijiria.

Ọba Makama to sọ eyi lasiko to n ṣe ijiroro pẹlu ileeṣẹ iroyin BBC ni ko si ijọba to le gbe ẹnu dakẹ ti awọn ajijagbara to fẹ da ilu ru bii Sunday Igboho ba dide.

O ni ẹnikẹni ti ijọba ba ti sọ pe awọn n wa, dandan ni ọwọ wọn yoo ba a.

Àkọlé fídíò, 'Nínú ìran, Olúwa sọ fún mi pé èmi ni màá tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ ìráńṣẹ́ Wòlìí TB Joshua, kàyéfì ti ń ṣẹlẹ̀ nínú ìjọ mi báyìí'
Àkọlé fídíò, 'Ẹ má jẹ́ kí òkú ọmọ mi ráre o ìjọba! Ẹ gbée fún mi kí n lọ sin ín - Ìyá ọmọ ti wọ́n pa ní ìwọ́de Yoruba Nation

''Ko si ẹnikẹni to n fi ipa gba ijọba lori ori ẹrọ ayelujara, awọn eniyan gbọdọ parapọ lati jiroro lori ohun ti wọn fẹ.''

''Gbogbo ariwo ti ẹ n pa lori ayelujara ko le doola ẹmi Sunday Igboho, ko si ẹni to le sa mọ ijọba lọwọ''

Bakan naa ni Ọba Olowu toi Kuta naa ni kii ṣe igba akọkọ ni yii ti ijọba ma n ṣekọlu si awọn ọta wọn ni oru.

Sunday Igboho

Oríṣun àwòrán, Others

Awọn adajọ ni ilu Abuja ti ijọba ṣekọlu si, oru ni wọn ṣe e

Awọn orilẹede lagbaye naa n lọ kaakiri lọru lati mu awn eniyan ti wọn ba n lepa, tabi ẹni ti wọn ba fẹ ṣe ikọlu si.''

Ninu ọrọ tirẹ, ọba ni oun ko fẹ Yoruba Natiopn nitori Niajiria dara papọ , amọ atunto Naijiria ni ọna abayọ si iṣoro to n koju orilẹede Naijiria.

Ọba Olowu ti Kuta, nipinlẹ Osun, Hammed Adekunle Oyelude Makama fikun wi pe Ọjọgbọn Banji Akintoye nikan niu oju mimọ to wa lẹyin Yoruba Nation, nitori Ẹgbẹ Afẹnifẹre to sọ gbogbo ọmọ Naijiria papọ sọ wi pe awọn ko fẹ iyapa lorilẹede Naijiria, yatọ si atunto.