Eid-el-fitr: Lẹ́yìn tí wọ́n rí òṣùpá, Sultan kéde ọjọ́ Ajé gẹ̀gẹ́ bíi ọjọ́ ọdún ìtúnu àwẹ̀

Oríṣun àwòrán, @MaryNoelBerje
Sultan ti ilu Sokoto, to tun jẹ Aarẹ igbimọ to n ri si ọrọ awọn Musulumi ni Naijiria, Muhammad Sa'ad Abubakar, ti kede ọjọ Aje, ọjọ keji, oṣu Karun un, ọdun 2022, gẹgẹ bii ọjọ ọdun itunu awẹ ni Naijiria.
Sultan lo sọ ọrọ naa ninu atẹjade kan, eyii ti Ọjọgbọn Sambo Junaidu, to jẹ alaga igibimọ to n ri si ọrọ ẹsin ni Sokoto buwọlu.
O ni igbimọ naa ko ri oṣupa ṣaaju kaakiri Naijiria, o si kede pe ọjọ Aiku ni yoo jẹ ọgbọn ọjọ oṣu Ramadan, iyẹn 1443AH.
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ ọkùnrin tó pa ọ̀rẹ́ rẹ̀ nítorí gbèsè tó jẹ ẹ́
- Mo bẹ̀rẹ̀ sí ń wọ ìjáàbù nítorí àwọn okùnrin máa ń wo bẹ̀bẹ̀rẹ́ ìdí mi tí mo bá ń wàásù - Sister Kate
- Afurasí Oníṣòwò ǹkan ìjà olóró méje kó sí pańpẹ́ Ọlọ́pàá ní Jos àti Taraba
- A kọ̀ láti yí ọkàn wà padà lórí ìpinnu Yorùbá Nation- Ilana Omo Oodua
- Òní ni ọjọ́ mẹ́jọ ìpapòdà Oba Lamidi Adeyemi ni ìlú Oyo
- Wòlíì Olubọla ni wọ́n fẹ̀sùn kàn pé ó jí ọkọ̀ ọmọ ijọ̀ lọ ní Abeokuta
Sultan ni oun ti gba iroyin wọn wọle, o si kede ọjọ Aje, ọjọ keji, oṣu Karun un, ọdun 2022 gẹgẹ bii ọjọ kinni Shawwal 1443AH, tii ṣe ọjọ ọdun itunu awẹ.
Lẹyin naa lo ba gbogbo awọn Musulumi ni Naijiria yọ, to si tun gbadura ibukun Ọlọrun fun wọn.
O tun rọ awọn Musulumi lati tẹsiwaju lati maa gbadura fun alaafia ati itẹsiwaju Naijiria.
Ki lo ti ṣẹlẹ ṣaaju?
Ramadan n tẹ̀síwájú lẹyìn tí oṣù kò fojú hàn ní Nàìjíríà àti Sáúdí

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ibẹrẹ ati opin awẹ Ramadan jẹ nkan ti ọpọ amaa foju sọna si.
Awẹ tọdun yi ti bẹrẹ ṣugbọn o ṣi ku diẹ ti yoo pari nitori awọn alaṣẹ musulumi ni Naijiria ati Saudi lawọn ko ri oṣu tuntun.
Ọsu tuntun yi to jẹ ti oṣu Shawwal ni onka oṣu oju ọrun musulumi lo jẹ atọna pe awẹ Ramadan ti pari.
Kaakiri loju opo ayelujara lawọn eeyan ti foju sọna de iroyin pe wọn yoo ri oṣu tuntun yi.
Koda igbimọ to gajulọ eleyi to n ṣakoso eto ẹsin Islam ti ni kawọn eeyan bẹrẹ si ni wa oṣu yi ṣaaju asiko yi.
Sultan ilu Sokoto,Alhaji Muhammad Saád Abubakar, to jẹ olori musulumi Naijiria lo fi ikede yi sita gba tẹnu igbimọ to n wa oṣu.
Amọ nigba ti yoo fi di irọlẹ mọ aṣalẹ ọjọ Abamẹta ikede jade pe wọn ko ti ri oṣu tuntun yi.

Oríṣun àwòrán, Facebook/nsciamoonsightingcommittee
Naijiria nikan kọ ni iroyin bayi ti jade.
Lorileede Saudi awọn igbimọ to n wa oṣu tuntun Ramadan nibẹ naa ti sọ pe toun ti bi oju ọjọ ṣe mọlẹ kedere awọn ko ri oṣu tuntun.
Eleyi waye lẹyin ti wọn ran awọn oniṣẹ lati lo irinṣẹ igbalode fi wa oṣu tuntun yi.

Oríṣun àwòrán, Haramain Sharifain
Ki wa ni airi oṣu yi tunmọ si fawọn alaawẹ
Ni ilana ẹsin Islaamu bi wọn ba ti wa oṣu Ramadan ti wọn ko ri, ohun to kan ni pe ki wọn ka oṣu Ramdan ko pe ọgbọn.
Loni tii ṣe ọgbọnjọ oṣu Kẹrin to ṣe deede ọjọ Kọkandinlọgbọn oṣu Ramadan ni wọn wa oṣu ti wọn ko ri.

Oríṣun àwòrán, HARAMAIN SHARIFAIN
Ko si ṣiṣe kan ko si aiṣe bayi ju pe ki awọn musulumi gba awẹ pe ọgbọn ki wọn si tunu ni ọjọ kini oṣu tuntun Shawwal.
Eyi tunmọ si pe ọjọ ọdun itunu awẹ ni Naijiria yoo maa jẹ ọjọ Keji oṣu Karun un ọdun 2022 tii ṣe ọjọ Aje.

Oríṣun àwòrán, Haramain Sharifain














