Child abuse: Bàbá ẹni ọdún 60 bá ọmọ ọdún méjìlá tó jẹ́ adití àti odi lòpọ̀, ó dèrò àtìmọ́lé

Ile ẹjọ kan ni Port Harcourt ti ni ki baba ẹni ọgọta ọdun kan lọ logba ninu ẹwọn titi di ọla ode yii lẹyin ti wọn fẹsun kan pe o fipa ba ọmọ ọdun mejila kan to jẹ odi lopọ.
Ṣaaju ni baba ọmọ naa ti kọkọ bẹ ile ẹjọ ọhun ko boju aanu wo oun ki oun le ri idajọ ododo gba lẹyin iṣẹlẹ naa.
Ẹka ileeṣẹẹ ọlọpaa to n ṣe iwadii iwa ọdaran, SCID, to wa niluu Port Harcoourt lo pe Afurasi naa lẹjọ lori ẹsun ti wọn fi kan ki adajọ majistreeti naa to ni ki wọn fi si ahamọ lọgba ẹwọn titi di ọjọ Aje ti yoo bẹrẹ igbẹjọ rẹ.
- Taa ni Firdauz Abdullahi, ọmọbabìnrin Kano, olòrì tuntun tó ń wọ Ààfin Oluwo lónìí?
- Òrùka táwọn òbìrin ń lò sí ojú ara rèé, mọ̀ síì nípa rẹ̀
- Wo tọkọ-taya kan ní Ukraine tó ń kọ́ ìṣẹ́ ológun nítorí ogun Russia
- Ẹ wo ìgbàradì l'Áàfin de Olorì tuntun Firdaus aya Oluwo ti Iwo
- Bí Tinubu bá fi lè di Ààrẹ, máa kúrò ní Nàìjíríà - Bode George
- Ìjọba àpapọ̀ ti gbé ìwé àlàyé jáde lórí àyípadà tí yóò bá iná ọba kó máa wá déédé
- Kí ló le fàá tí àwọn ọlọ́pàá fi ń wá ẹranko Bíárì ládùúgbó? Àlàyé rèé
- Wo àwọn àṣìṣe ikọ̀ ológun Russia ní Ukraine
- Àwẹ̀ àti àdúrà ló gbé mi dé orí ètò 'Nigerian idol' gẹ́gẹ́ bíi alákòso - D’Banj
Bi ọwọ ṣe tẹ afurasi naa
Baba ọmọ ti afurasi ọhun ba lopọ, Eze Eleonu sọ pe korokoro bayii ni ọwọ oun tẹ afurasi naa ni ihoho ọmọluabi pẹlu ọmọ oun.
O ni inu ile oun ni ọwọ oun ti tẹ pẹlu ọmọ oun lọjọ karun un, oṣu Kẹta, ọdun yii.
Eleonu sọ pe ni kete ti oun ri bayii ni oun kigbe ibosi ara adugbo, ti awọn eeyan si ku giri wa sibẹ.
Lẹyin naa ni wọn fa a le fijilante lọwọ, ti awọn naa si mu lọ si agọ ọlọpaa to wa ni Ubima.
Ijiya biba ọmọde lopọ
Ni Naijiria, ẹṣẹ ni labẹ ofin lati ba ọmọde ti ọjọ ori rẹ ko tii ju ọdun mejidinlogun lọ lopọ.
Ẹnikẹni to ba jẹbi ẹsun naa le fi ẹwọn gbere jura.
Amọ, yatọ si ẹwọn gbere, awọn ipinlẹ ni Naijiria naa ni oniruru ijiya fun ẹsun naa.














