Àwọn ǹkan tí ẹ kò mọ̀ nípa Ìjàpá Ogbomoso kó tó kú

Akọwe Toyin Ajamu
Àkọlé àwòrán, Akọwe Toyin Ajamu pẹlu Ijapa Ogbomoso
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Lẹ́yìn tí Ijapa to dagba ju nilẹ Afirika yii dagbere faye lẹni ọdun mejilelọọdunrun, ile iṣẹ BBC ṣewadii awọn nkan to laami laaka nipa rẹ.

Gẹgẹ bí awọn akọṣẹmọṣẹ atawọn onimọ nipa itọju ẹranko ṣe sọ ọ, aaringbugbun gbekede ti ijapa n lo laye ni aadọjọ ọdun bẹẹ si ni eyi ti eeyan ti ri ri to ju bẹẹ lọ ṣaaju ti Alagba ni o lo Igba ọdun laye.

Ẹwẹ, Alagba ṣe o lo odidi ọdun mejilelọọdunrun loke eepẹ ko to faye silẹ.

Lara ohun ti ẹ ko mọ nipa oloogbe ijapa to wa lafin Ṣọun Ogbomoso ree.

Agba Inaki n ṣe'daro Alagba

Skip X post
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post

Àkọlé fídíò, Ogbologbo ijapa l'aafin Sọun
Àkọlé fídíò, Imam tó ṣí Mọ́ṣálásì fáwọn Krístẹ́nì sọ ìdí tí kò fi lè ta wọ́n nù
  • Ijapa Ogbomoso dagba ju gbedeke iye ọjọ ori tawọn onimọ ni o yẹ ki Ijapa kan lo laye lọ.
  • Wọn ko gun un ni abẹ́rẹ́ ri tabi ki awọn onimọ iṣegun oyinbo ṣe ayẹwo fun un ri.
  • Ẹẹmeji pere ni Alagba maa n jẹun laarin oṣu kan kii sii sunmọ ẹnu ibode ọgba rẹ ayafi bo ba fẹ mu omi. Eyi ni wọn fi n mọ pe omi lo fẹ.
  • Awọn eeyan a ma lọ sọdọ ogbologbo Ijapa yii lati tọrọ ẹbẹ adura to si n wa si imuṣẹ

Àwọn àrídájú 'ọ̀rọ̀ yìí wá látẹ́nu akọ̀wé àgbà Toyin Ajamu ní ààfin Kábíyèsí Ṣọun ti ilu Ogbomosho fún BBC Yorùbá.