Abeokuta Ritual Killing: 'Colour Ghana Must Go' ló tú àṣírí Tọkọtayà náà níbi tí wọ́n kó ifún ọ̀rẹ́ ìyàwó tí wọ́n pa tà náà sí- Baale Leme

Àkọlé fídíò, Abeokuta murder

Omi ló wa loke ike naa, ko si nkan mii nibẹ ni ariwo ti ọkọ iyawo naa n pa fun wa nigba ti a fẹ tu iyara wọn wo- Baale Leme ni abeokuta ni ipinle Ogun

Se ẹ ranti Tokotaya ti wọn ba ifun eeyan ninu ike ninu iyara wọn ni agbegbe Abeokuta ni guusu Iwo oorun Naijiria?Afurasí tọkọtaya ta ẹ̀yà ara fún ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́rin náírà- Ọlọ́pàá

BBC Yoruba ti de ibẹ lati mu ohun to ṣẹlẹ gangan wa fun un yin ki onikaluku le kọ ẹkọ bi o ti yẹ.

Bawo ni ọrọ ṣe ṣẹlẹ gangan?

Alhaji Moshood Ogunwoolu to je Baale agbegbe Lemo ni Abeokuta lo ba BBC Yoruba sọrọ lori bi wọn ṣe ri oku naa lọna meji.

Baale naa ni pe ọkọ iyawo ti ọwọ tẹ naa sọ pe iṣẹ Babalawo ni oun n ṣe jẹun.

Okọ ilu ni pe apa ati aya ati ẹsẹ ti wọn ba ninu apo aromiyọ iko nkan pamọ si ti awọn kan n pe ni "Ghana Must Go" lẹgbẹ odo ni wọn ti kọkọ ri.

Baale naa ṣorọ ilẹ kun lori bi awọn Tokotaya yii ṣe ko ifun ati ẹya ara ọrẹ iyawo to ku naa pamọ sinu ike ti wọn pọn omi sii ati ipa ti awọn ara ile, ara adugbo ati ara abule naa ko lori iṣẹlẹ yii.,

Oyeyemi

Kini Oga ọlọpaa ri sọ si ọrọ naa?

Oga Olopaa Abimbola Oyeyemi naa ba BBC Yoruba sọrọ lori iṣẹlẹ naa.

O salaye ibi ti iṣẹ iwadii ti de bayii ati pe ijiya to tọ yoo jẹ awọn Tokotaya yii ni kete ti ẹjọ ba ti pari lori ọrọ naa.

Bakan naa lo gba awọn eeyan nimọran lati ma dagbere ibikibi ti won ba n lo lasiko yii nitori pe : Mo n bọ kii ṣe adireẹṣi ti eeyan le wa ẹni to sọnu si o.