2021 Twin Festival: Aráàlú ní Ifá ló sọ pé ìbejì yóò pọ̀ ní Igboora, kìí ṣe jíjẹ Ìlasa
Ajọdun ọdun ibeji to waye ni ọdun 2021 dun, to si larinrin pupọ nitori awọn eeyan jankan-jankan to peju sibẹ, to fi mọ Alaafin tilu Oyo, Oba Lamidi Olayiwola Adeyemi Kẹta.
Ninu ifọrọwerọ ti BBC Yoruba se fawọn ibeji ati araalu ni wọn ti salaye idi ti awọn ibeji se pọ silu Igboora ati ohun to fa sise ajọdun naa lọdọọdun.
Lara awọn ibeji to ba BBC Yoruba sọrọ lo koro oju si bi awọn obi kan se maa n gbe awọn ibeji jo kiri lati se agbe jẹun.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Chiwetalu Agu ti gba òmìnira lọ́wọ́ àwọn sọ́jà tó mú u
- Agbébọn jí ìbejì ọba gbé àti èèyàn mẹta míì ní Kwara
- Bimbo Oshin ṣàlàyé ọ̀rọ̀ ìkẹyìn tí ọkọ rẹ̀ sọ fun un kó tó kú
- Wo àwọn ohun mẹ́jọ́ tí àwọn olólùfẹ́ gbọ̀dọ̀ ṣe lẹ́yìn ìbálòpọ̀
- Ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa Ọ̀jọ̀gbọ́n Oyebode Adebowale, gíwá tuntun ní fásitì Ibadan
- Godwin ṣá bàbá rẹ̀ ládá pa nítorí orí adìyẹ, Ó ní...
- Ẹ wo bí arákùnrin kan ṣe fi ọrún àti ọfà pa èèyàn márún ún
- "Olórí ọmọ ogun Islamic State ní Ìwọ̀ Oòrùn Afrika, ISWAP ti jáde láyé"
- Sàdáńkátà! Ẹ̀yin ẹ̀létò ààbò, mo dúpẹ́ lọ́wọ́ yín fún ìkọlù sí ilé Sunday Igboho - Ààrẹ Buhari
- Àwọn afurasí gbin ǹkan olóró abúgbàmù sí ṣọ́ọ̀ṣì bàbá Wike, ọwọ́ pálábá wọ́n ségi!
Awọn ibeji naa ni eyi ko dara to rara nitori awọn ibeji kii se olosi tabi alagbe ọmọ, ti wọn si n ke si ijọba lati se ofin ti yoo pa asa naa rẹ.
Bakan naa ni awọn araalu sọ pe ero awọn eeyan kan to ni bi wọn se maa n jẹ ọbẹ Ilasa to wọpọ julọ nilu Igboora, lo mu ki wọn maa bi Ibeji ko tọna rara.
Awọn kan ni Ifa lo ti kọkọ kede saaju pe ilu naa yoo gbajumọ fun bibi Ibeji lorilẹ aye, eyi to n wa si imusẹ bayii.
Awọn miran ni eeyan le jẹ ọbẹ Ilasa lai ma bi ibeji amọ ti eeyan ba mu omi ilu Igboora sori ounjẹ naa, eroja mejeeji yii ni yoo parapọ lati mu ibeji wa.
Ẹkunrẹrẹ fidio bi ọdun ibeji se lọ nilu Igboora lọdun 20121 ree, ẹ wo o.




