Saidu Abdullahi: Ó kúrò nílé lẹni ọdún mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n, lẹyìn ọgọ́ta ọdún ló bá ṣadede yọ sí ìlú padà'

Aworan baba agbalagba ti o pada sile lẹyin ọgọta ọdun

Njẹ ẹyin ti ri ibi ti eeyan ti dawati fun ọgọta ọdun ri amọ to tun ṣadede foju han pada si awọn araale rẹ?

Ọrọ yii da bii fiimu ṣugbọn kii ṣe awada rara.

Ni ilu kan ti wọn n pe ni Dakatsalle ni ijọba ibilẹ Bebeji nipinlẹ Kano, ni iroyin kayeefi yii ti ṣẹlẹ.

Niṣe ni wọn tu yaya sita lati wa wo baba agbalagba kan, ti o pada wale lẹyin ọgọta ọdun ti o dawati.

Àkọlé fídíò, OAU student's death: O dun OAU pé Heritage kú, agbìyànjú láti gbé e délé ìwòsàn ṣùgbọ́n...

Ki lo gbe Baba pada wa sile?

Ọgọta ọdun lẹyin ti Mallam Saidu Abdullahi file silẹ lẹni ọdun mẹrindinlọgbọn, ṣadede ni wọn ri to pada wale lagbalagba.

Ki ọrọ yii baa le ye wa daada, ko pẹ si igba ti Naijiria gba ominira ni o file silẹ, to si sọ fun akọroyin BBC pe ọkan oun ti n fa ile ṣugbọn oun ko ribi pada wa sile.

Akọroyin BBC Khalifa Shehu Dokaji to ṣabẹwo si idile Saidu jabọ pe awọn ọmọ, mọlẹbi, ọmọọmọ ati awọn alabagbe pe biba, lati wa ba wọn yọ pe o pada wa sile.

Nibo ni Baba ha si lati ọjọ yii?

Ilu Ibadan ni iṣẹ aje gbe Saidu Abdullahi lọ, nibi to ti n ṣe òwò Awùsá.

A tun gbọ pe iya rẹ lo gba a niyanju lati tọ ẹgbọn baba rẹ kan lọ nigba ti o wa ni ẹni ọdun mẹrindinlọgbọn.

Gẹgẹ bo ti ṣe ṣalaye fun BBC, nigba aye Emir Abdullahi Bayero to jẹ baba baba Emir Kano to wa lori oye lo ni oun ti kuro nile.

Ni igba taa n sọ yii, wọn ko tiẹ ti lala pe wọn yoo da ipinlẹ Kano silẹ rara.

Iṣiro ọdun taa n wi yii wa laarin ọdun 1926 -1953.

Pupọ ninu awọn mọlẹbi lo ti sọ ireti nu, koda awọn miran ro pe o ti ku ni.

Ohun iyalẹnu kan ni pe ede ẹnu rẹ ko yipada ati pe arugbo ko ni ko ma mọ ohun to n ṣẹlẹ lawujọ.

Àkọlé fídíò, Wòólì Alfred kú lọ́dún 1964, ó tún padà wà sí ìlú Agelu f'ọ́jọ́ mẹ́rìnlá!