Bola Tinubu: ''Ìròyìn òfegè lásán ni! Tinubu kò lùgbàdí coronavirus''

Oríṣun àwòrán, Facebook/Asiwaju Bola Tinubu
Faabada! Gomina ipinlẹ Eko tẹlẹ, Aṣiwaju Bola Tinubu ti sọ pe ahesọ lawọn kan n gbe kiri pe oun ti karun coronavirus.
Ọrọ naa ti lu ori ayelujara pa pe Tinubu ti lugbadi covid-19, o si n gba itọju lọwọ nile iwosan lorilẹede Faranse loke okun.
Ṣugbọn Tinubu to gba ẹnu oluranlọwọ rẹ, Tunde Rahman sọrọ ṣalaye pe igba mẹẹdogun loun ti ṣe ayẹwo fun covid-19 eleyi to si ja si pe ṣaka lara oun da.
- Sunday Igboho sọ̀rọ̀ lórí ohun tó kan fún ilẹ̀ Yorùbá lọ́dún 2021
- Ìjọba ní kí kọmíṣọ́nnà àyíká ìpínlẹ̀ Ogun lọ rọ́kún ńlé lórí ẹ̀sùn ìyọnilẹ́nu torí ìbálòpọ̀
- Pásítọ̀ Adeboye bú ẹnu àtẹ́ lú ìjọba tó fofin dé ìsìn ìrékọjá sí ọdún tuntun
- Àwọn ànfààní tó wà nínú ìbálọ̀pọ̀ fún ọkàn àti ara rẹ
- Mí ò gba àbẹ́tẹ́lẹ̀ rí ní ọgbọ̀n ọdún ti mo fi ṣíṣẹ́ ọlọ́pàá- CSP Francis Osagie
- Èsíò! Manchester City gba fújà lọ́wọ́ Chelsea n'íbẹ̀rẹ̀ ọdún tuntun
Ọgbẹni Rahman ni irọ funfun balau lati ọrun apaadi ni iroyin ọhun.
''Koko lara Asiwaju le, ko si ṣaisan, bẹẹ ni ko ni arun coronavirus,'' Rahman lo sọ bẹẹ.
Ọgbẹni Rahman sọ pe lootọọ ni Tinubu ko si ni Naijiria lọwọ yii, ṣugbọn o ṣalaye pe ilẹ Faranse kọ ni Asiwaju wa gẹgẹ bi iroyin kan ṣe sọ lori ayelujara.
''Ilu London ni Tinubu wa, kii ṣe orilẹede Faranse gẹgẹ iroyin ẹlẹjẹ ṣe sọ lori ayelujara,'' Ọgbgẹni Rahman ṣalaye.








